You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Itan Manigbagbe: Olorì Luwoo, Gbàgìdí jẹ́ obìnrin tó ṣáájú àsìkò rẹ̀ jẹ Ooni Ife tó sì tún jẹ́ alágbára gidi nílẹ̀ Yorùbá
Olorì Luwoo, Gbàgìdí jẹ́ obìnrin tó ṣáájú àsìkò rẹ̀ jẹ Ooni Ife tó sì tún jẹ́ alágbára gidi nílẹ̀ Yorùbá
Olorì Luwoo, Gbàgìdí jẹ́ obìnrin tó ṣáájú àsìkò rẹ̀ jẹ Ooni Ife tó sì tún jẹ́ alágbára gidi nílẹ̀ Yorùbá.
Gẹ́gẹ́ bí ìtàn ṣe sọ ó rẹwà púpọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìtàn ṣe sọ, ẹwà yìí a sì máa jẹ́ ìwúrí fún pẹ̀lú.
- Ọba Lamidi Adeyẹmi, òṣìṣẹ́ adójútòfò àti Abẹ̀ṣẹ́kùbíòjò kó tó jọba
- Oyinkan Abayomi, akọni obìnrin tó fi ìfẹ́ pa orúkọ ọkọ kejì dà sí ti ọkọ àárọ̀
- Wo àwọn sinimá mẹ́wàá tó gbé sinimá Yorùbá sáyé
- Wo awọn iroyin manigbagbe to waye ni ọsẹ yii
- Àwọn Ọba Yorùbá kan rèé tí wọ́n rọ̀ lóyè, tí ọba míràn jẹ lójú ayé wọn
Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìtàn to pọ̀ lóde kò fi bẹ́ẹ̀ dárúkọ rẹ̀, nítorí pé ìtàn àtẹnudẹ̀nu ló pọ̀jù nínú ìtàn orile-ede Naijiria, ọ̀pọ̀ sí ló máa ń sọ ìtàn bí ẹni pé ọkùnrin nìkan ló n jẹ Ooni Ife.
Luwoo jẹ́ ọba Ọ̀ọ̀ni ìkọkanlélógún ni sẹ́ntúrì kẹwàá, òun ló jẹ lẹ́yìn ọba Gẹ̀ẹ́sì ti Ọ̀ọ̀ni Lumobi sì jẹ lẹ́yìn rẹ̀.
Nínú àkọsílẹ̀ kan, a gbọ́ pé wọ́n n pè é ní Luwoo Gbàgìdí nítorí o jẹ́ ọmọ bíbí Otaataa láti ìdílé Owode Okerewe, ó sì fẹ́ olóyè Obaloran ti Ilode, Elédùà fi Adekola Telu tó jẹ́ ẹni tó tẹ ìlú Iwo dó.
- Iléeṣẹ́ ológun Myanmar ti di ojú òpó facebook pa kí ọkàn àwọn ará ìlú lè balẹ̀
- Àwọn ẹ̀gbọ́n mi ọkùnrin dá pín ogun bàbá wa, wọ́n ní pé obìnrin ni mí- Onyinye
- Irọ́ ní o, a kò buwọ́lu Goodluck Jonathan fún ipò ààrẹ 2023 - APC
- Ṣọun Ogbomọṣọ àti Sunday Dare gbóríyìn fún Buhari lórí 'Polytechnic' Ayede Ogbomoso
Lẹ́yìn ti Ọ̀ọ̀ni Geisi kú, òun ni obìnrin láti gorí àpèrè gẹ́gẹ́ bí Ọ̀ọ̀ni.
Nítorí pé Ọ̀ọ̀ni yìí rẹwà púpọ̀, tí èyí si máa n mú inú rẹ̀ dùn ní gbogbo ìgbà mu ki àwọn ará ìlú Ife àti ọkùnrin àti obìnrin máa sapá wọ́n láti mu kí àyíká wọ́n rẹwà gidi kí ó sì dùn wò.
Nítorí pé Ọ̀ọ̀ni Luwoo ko fẹ́ràn láti máa tẹ iyanrìn lásán, nítorí rẹ̀ ló ni kí wọ́n ṣe àwọn pèpéle (ó ti di ti àwọn ilé ìkó ǹkan ìṣẹ̀mbáyé Ife si),pẹ̀lú àwọn ǹkan ọ̀gbìn tó rẹwà láti fi mú àyíká rẹ̀ dùnwò.
Lílo àwọn iṣẹ́ ọ̀nà amọ̀ láti fi ṣe àyíká rẹ̀ lọ́jọ́ àti gbogbo ilẹ̀ Yorùbá to bá ṣe àbẹ̀wò sí jẹ àbùdá adámọ́ tí wọ́n mọ̀ ọ́ sí.
Bákan náà lo má n ló o láti fi jẹ́ ẹnikẹ́ni to ba rúfin níyà láti ṣe Irúfẹ́ rẹ̀ sí àwọn òpópónà ilé ìfẹ́ pẹ̀lú òkúta akọ àti àwọn afọ́kù kòkò amọ̀.
Àwọn tó bá jẹ́ ọmọ ìta ló máa ń lò láti sún amọ̀ tí yóò sì ni kí wọ́n fi ọwọ́ wọn lásán fọ́ọ pada, wọ́n yóò wá tòó sí ojú ọ̀nà tí Ọ̀ọ̀ni yóò gbà kọjá.
Yàtọ̀ sí èyí ẹ̀rù jẹ̀jẹ̀ ni fáwọn ọkùnrin nítorí ìtàn sọ pé, ó kórira ọkùnrin tó bá n ṣe ìmẹ́lẹ́ tó tú n rúfin.
- Àwọn ẹ̀gbọ́n mi ọkùnrin dá pín ogun bàbá wa, wọ́n ní pé obìnrin ni mí- Onyinye
- Irọ́ ní o, a kò buwọ́lu Goodluck Jonathan fún ipò ààrẹ 2023 - APC
- Kábíyèsí Ooni ti forí jin Sunday Igboho lẹ́yìn tó túúbá- Ààfin Ile Ife
- Aàrẹ Joe Biden yóò so àwọn ẹbí ti ìjọba Trump túka papọ̀.
- Ọkùnrín márùn ún fojúbalé ẹjọ́ lórí ẹ̀sùn ijà àti igbó fífà ní gbangba
Láyé Luwoo, kò sí ìyàtọ̀ nínú ẹrú àti ọmọ, bákan náà ni ó ṣe máa n ṣe sí wọn.
Àwọn àgbààgbà ìlú rí wípé apá ò ká Luwoo mọ́, o si tún jẹ́ apàṣẹ wàá, wọ́n gbìmọ̀ pọ̀ lẹ́yìn tí àsìkò tirẹ̀ parí pé obìnrin kankan kò ní jẹ Ọ̀ọ̀ni mọ́.
Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ìgbìmọ̀ ọba tí wọ́n fún Luwoo ni orúkọ burúkú yii náà ló rán Ọmọkùnrin rẹ̀ Adekola Telu lọ́wọ́ láti tẹ ìlú Iwo dó, ti o sì jẹ́ Oluwo tí ìlú Iwo àkọ́kọ́.
- Wo ìdí tí ìjọba Buhari fi ti àkáúǹtì àwọn tó ń ṣe kátà kárà owó ''cryptocurrency'' pa
- Ta ló pa ẹbí olùrànlọ́wọ́ Gómìnà Rotimi Akeredolu nínú oko rẹ̀ l'Ondo?
- Wo àwọn gbajúgbajà ojú ti EFCC máa ba ṣe ẹjọ́ ní 2021
- Ẹ rọra ṣe pẹ̀lú àwọn ará ìlú lásìkò yìí nítorí Covid 19- IGP Adamu Mohammed
- Ṣọun Ogbomọṣọ àti Sunday Dare gbóríyìn fún Buhari lórí 'Polytechnic' Ayede Ogbomoso