Fasoranti: Àwọn ọ̀dọ́ Ondo fárígá lórí ikú Funke Olakunrin
Àwọn ọ̀dọ́ ipinlẹ Ondo tu sita lati fẹhonu han lori ọpọ ọsẹ ti awọn to n pa eeyan ni ipinlẹ wọn paapaa nigba ti awọn ba n rinrinajo.
Lẹyin ti awọn agbebọn pa Funke Olakunrin to jẹ ọmọ adari ẹgbẹ Afẹnifẹrẹ lorilẹ-ede Naijiria, iṣẹlẹ naa wu ọpọlọnu irunu jade lọdọ awọn ọmọ Naijiria.
Lara eyi naa lo mu ki awọn ọdọ ipinlẹ Ondo figbe ta pe o ti to gẹ pe ki awon Fulani kuro lagbegbe awọn, tori awọn kan n sọ wi pe awọn lo wa nidi iku rẹ.
Adekanbi Oluwatuyi to jẹ olori ọdọ ni gbogbo ilu Akure sọ fun BBC Yoruba pe gbogbo agbaye mọ pe iṣẹ agbẹ lo wọpọ ju lagbegbe awọn ṣugbọn gbogbo eniyan lo ti sa kuro l'oko.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Laduntan Oyekanmi di ìyálóde tuntun fún ilẹ̀ Ibadan
- Ìtàn tó wà nídi òwe ‘Sebótimọ Ẹlẹ́wà Sàpọ́n’
- Taiwo Akinkunmi, ọmọ Ibadan tó ya àsìá Nàíjíríà
- Ogedengbe Agbógun Gbórò, Akọni tó ń dẹ́rù ba ikú...
- MKO Abiola, iṣẹ́ aṣẹ́gità ló fi bẹ̀rẹ̀ okoòwò
- Iṣọla Oyenusi rèé, ẹnití ìfẹ́ obìnrin ṣun dé ìwà ìdigunjalè
- Taiwo Akinkunmi, ọmọ Ibadan tó ya àsìá Naijiria
- Ayinla Ọmọwura, orin èébú àti oríyìn lo fi di ọ̀rẹ́ àwọ̀n obìnrin
- Ìtàn tó rọ̀ mọ́ òwe ‘aṣọ kò bá Ọ́mọ́yẹ mọ́...’ rèé
Ṣe ni wọn n tẹnu mọ ọ pe awọn Fulani darandaran ti gba gbogbo ilu awọn tan wọn si ti n ke si ijọba titi titi ti ko si oun ti ijọba ṣe.
Olori ọdọ ni ohun to ku tawọn yoo ṣe ni ki onikaluku maa ja funra wọn.