Election Tribunal: À ó lọ ilé ẹjọ kòtẹmilọrùn - Ayodele Fayose

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

Lẹ́yìn ìdájọ ilé ẹjọ́ tó ń ri si ẹsùn abájade ètò ìdìbò ti dá Kayode Fayemi ni oriṣiiriṣii ọrọ n jade.

Fayẹmi to dije lẹgbẹ òṣèlú All Progressives Congress (APC) ko to jẹ Gomina Ipínlẹ̀ Ekiti ni wọn da láre gẹ́gẹ́ bíi ojúlówo ẹni to jáwé olúbori nínú ìdìbò tó waye lọ́dún tó kọja.

Gómìnà Ipínlẹ̀ Ekiti nígbà kan rí Ayodele Fayose tí Olúsọla Eleka lábẹ́ ẹgbẹ́ òṣèlú People's Democratic Party (PDP) jẹ ìgbákeji fún ti fi atẹ̀jíṣẹ́ léde lóri twitter rẹ̀ lẹ́yìn èsì ìgbẹjọ́ náà.

O ní ìyàlẹ́nu ní kò bá jẹ́ fún òun tí kò ba lọ bí ó ṣe lọ nítorí kii ṣe àjòjì sí ẹnikẹni gẹ́gẹ bí ó ṣe jẹ́ ọwọ ijọba tó ń bẹ lóde.

O fí kún un pé ọ̀pọ́ àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú APC ló tí ń ṣe ajọyọ lóri abajade ìgbéjọ́ náà.

Àwọn ọmọ Nàìjíríà tí ń fi èrò wọn hàn lórí ọ̀rọ̀ ti Fayose sọ

"Mo rọ ẹyin ọmọ Naijíríà àti Ekiti kí ẹ si ní ìrètí pé gbogbo ìwà ìjẹ̀gàba lọ́wọ́ àwọn adájọ àti ilé ẹjọ kò ní pẹ dópin."

O ní jú gbogbo rẹ̀ lọ ou fẹ kí oludíje lábẹ́ àsíá ẹgbẹ́ ọjọgbọ̀n Olusola Eleka. " ó ti pọndandan kí ó ṣe aṣeyori."

" À ó gbé ẹjọ́ náà lọ sí ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn àti ilé ẹjọ́ to ga jùlọ ti ó si ti pọndandan ki a jáwé olúbori"