Ayajọ iranti awọn akọni: Ayẹyẹ waye kaakiri orilẹede Naijiria

Oríṣun àwòrán, LASG
Lọjọ aje tii se ọjọ kẹẹdogun osu kini ọdun 2018 ni ayajọ ọjọ iranti awọn ologun to subu loju ija waye kaakiri tibu-toro ilẹ Naijiria.

Oríṣun àwòrán, EMMANUEL OLOYEDE
Ni ẹkun iwọ oorun guusu awọn ipinlẹ bii Ondo, Ọyọ, Ọsun, Ekiti pẹlu ko gbẹyin ninu sise ayajọ naa.

Oríṣun àwòrán, EMMANUEL OLOYEDE
Ni ipinlẹ Ọsun, Gomina Arẹgbẹsọla to saaju tito ododo soju ẹyẹ awọn akọni ni akoko to latubọ yanana isọkan ati aabo lorilẹede Naijiria.

Oríṣun àwòrán, Alamy
Gomina ana nipinlẹ naa, Ọmọọba Ọlagunsoye Oyinlọla pe fun atunyẹwo ilana isẹ awọn abọde ologun ti wọn fara jiya loju ija fun isọkan ilẹ Naijiria.

Oríṣun àwòrán, OPE OLAWALE
Ni ipinlẹ Ondo, gomina Rotimi Akeredolu ke si awọn agbofinro gbogbo lorilẹede Naijiria lati tubọ ji giri si ipenija ti gulegule wahala awọn darandaran nko ba eto abo.

Oríṣun àwòrán, OPE OLAWALE
Ni ipinlẹ Ọyọ, Gomina Ajimọbi dupẹ pupọ lọwọ awọn oloogun ilẹ Naijiria fun diduro sinsin fun isọkan ati alaafia araalu.

Oríṣun àwòrán, CONNECT








