Òṣèré tíátà Yoruba míì, Adewale Adeyemo jáde láyé

Gbajugbaja oṣere tiata Yoruba, Adewale Adeyemo ti jade laye.

Gẹgẹ bii ohun ti a gbọ, aarọ ọjọ Aje, ọjọ kejilelogun, oṣu Karun un, ọdun ti a wa yii ni oloogbe naa jade laye.

Akẹgbẹ rẹ nidi iṣẹ tiata, Ronke Oshodi Oke, lo kede iku rẹ loju opo Instagram rẹ.

Ronke ni “Hmmm oga bayii ooo... a fẹran rẹ amọ Ọlọrun fẹran rẹ ju wa lọ.”

“Sun re o Adewale Adeyemo.”

Iṣẹlẹ yii lo n waye lẹyin nnkan bii ọsẹ kan ti gbajumọ oṣere tiata Yoruba, Murphy Afolabi jade laye.

Awọn oṣere tiata ṣi n ṣedaro Murphy Afolabi lọwọ ti iroyin iku Adewale Adeyemo yii tun gbode kan.

Aisan kidirin at ẹdọforo yọ Adewale lẹnu ṣaju iku rẹ

Ti ẹ ko ba gbagbe, ṣaaju ni Adewale ti kọkọ n ṣaisan, to si bere iranlọwọ owo lọwọ lawọn eeyan lọdun naa lọhun.

Iroyin ni aisan ọgbẹ inu lo ro pe o n da oun laamu tẹlẹ amọ ayẹwo fi han lọdun 2020 pe aisan kidirin ati ẹdọforo lo n damu rẹ.

Lẹyin naa ni awọn ẹlẹyinju anu da owo jọ fun lati ṣiṣẹ abẹ.