Wo iṣẹ́ tí Tinubu, Osinbajo àti Buhari rán sí àwọn ọmọ Naijiria lọ́jọ́ 'Good Friday'

Aarẹ Naijiria ti wọn ṣẹṣẹ dibo yan, Bola Ahmed Tinubu ti ki awọn araalu ku ayẹyẹ ọdun Ajinde.

Ninu ọrọ to fi lede loju opo Twitter rẹ ni Tinubu ti fi ikini naa ranṣẹ.

O ni “A ku ayẹyẹ ọdun ‘Good Friday.’”

Yatọ si Tinubu, Aarẹ Muhammadu Buhari naa tun fi ọrọ ikini ranṣẹ loju opo Twitter rẹ.

Buhari sọ pe “Mo darapọ mọ awọn Kristẹni ni Naijiria ati kaakiri agbaye lati ṣajọyọ ọdun Ajinde, eyii ti n ṣe iranti iku ati ajinde Jesu Kristi ati iṣẹgun rẹ lori iku.”

O ni asiko ọdun naa n ṣe iranti pe ko si ohun ti Ọlọrun ko le ṣe, O si le yi ohun buruku pada si daadaa.

Lẹyin naa lo rọ awọn araalu lati má sọ ireti nu lori pe Naijiria ṣi maa dara.

Yemi Osinbajo, to jẹ igbakeji Aarẹ Naijiria naa ni “Fun gbogbo awọn to gbagbọ pe ẹjẹ Jesu ti san gbogbo gbegbe ẹṣẹ wọn lori igi agbelebu.... a ku ọdun ‘Good Friday.’”

Gomina Eko, Babajide Sanwo-Olu naa fi ọjọ ‘Good Friday’ ọhun ke si awọn eeyan ipinlẹ rẹ lati daabo bo ara wọn atawọn ọmọnikeji wọn.

Bẹẹ naa lo tun fi akoko naa gba awọn araalu niyanju lati fẹran ọmọnikeji wọn gẹgẹ bii ara wọn.