You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́
Ẹ dákun ẹ dábọ̀, ẹ fiyè dénú
Ìjọba Nàìjíríà ló rawọ́ ẹ̀bẹ̀ sí Amẹ́ríkà lórí àtúnṣe gbígba físà tí wọ́n gbé jáde lọ́jọ́ Ìṣẹ́gun
Iléeṣẹ́ tó ń rí sí ọ̀rọ̀ ilẹ̀ òkèèrè ní Nàìjíríà sọ pé
Ìgbésẹ̀ náà lòdì sí ìbáṣepọ̀ tó wà láàárín orílẹ̀ èdè méjéèjì
xxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxx
Ilé ẹjọ́ tó ga jùlọ ní Nàìjíríà, Supreme Court ti fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé
Gómìnà ìpínlẹ̀ Edo, Monday Okpebholo ni ojúlówó gómìnà tí wọ́n dìyàn díbò yàn
Adájọ́ Mohammed Lawal Garba nígbà tó ń gbé ìdájọ́ kalẹ̀ sọ pé
Ẹgbẹ́ òṣèlú PDP àti òṣèlú kò fìdí ẹ̀sùn wọn múlẹ̀ tó lórí ẹjọ́ tí wọ́n pè tako Okpebholo àti APC
xxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxxx
Ìjọba ìpínlẹ̀ Ogun àfọ̀mọ́ ọ̀rọ̀
Lórí ọkùnrin kan, Ogbonna Ogbojionu tó ní wọ́n dájọ́ ikú fóun nítorí òun ra ẹ̀rọ jẹnẹrétọ̀ tí wọ́n jí gbé
Àmọ́ Kọmíṣánnà fétò ìdájọ́ ìpínlẹ̀ Ogun, Oluwasina Ogungbade sọ pé irọ́ ló pa àti pé
Ogbonna wà lára àwọn tó lọ ja ilé epo kan lólè lọ́dún 2000 níbi tí wọ́n ti pa èèyàn kan