You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́
Kaka kewe agbọn dẹ, niṣe lo n le koko si lọrọ iwa ajẹbanu ni Naijiria o
Ki lo tun ṣẹlẹ?
Ajọ EFCC lo ma ti gbẹsẹ le ilegbe 753 nilu Abuja lọwọ oṣiṣẹ ijọba kan
Haha! Iyẹn tun gbẹnutan o. Ta ni wọn wa gba awọn ile ọhun lọwọ rẹ?
Ti o ba fẹ mọ, kan soju opo BBC.Com/Yoruba
Ọjọ buruku Eṣu gbomi mu
Lonii lo pe ọdun kan ti ileeṣẹ ọmoogun Naijiria ṣeesi ju ado oloro si abule Tudunbiri lapa Onipinlẹ Kaduna
Eyi to ṣeku pa ọpọ eeyan lasiko ayẹyẹ ọdun Mawludi awọn musulumi lọdun to kọja
Awọn ara abule ọhun ni iṣẹlẹ naa si n fun awọn ni ibanujẹ ọkan titi di akoko yii
Ẹni ọrẹ da ko ma fi ṣe ibinu, ẹni abinibi n da ni
Gbajugbaja oṣerebinrin, Ronke Odunsanya ti sọ pe ọrẹ oun timọtimọ kan
lo duro gẹgẹ bi eṣu lati da igbeyawo oun ru
Ronke tọpọ eeyan mọ si Flakky Ididowo ni oun ko le gbagbe iṣẹlẹ naa laelae
tori ibanujẹ lo maa n jẹ foun ni gbogbo igba