Kò ṣe é mà gbọ̀ ọ́

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 2

Họwu! Họwu l'Abuja

Ki lo n ṣẹlẹ nibẹ?

Igun olufẹhonuhan meji ti gbogbo wọn jẹ obinrin lo maa doju kọ ara niwaju ile aṣofin agba l'Abuja lonii

Ki ni wọn lo ṣẹlẹ?

Àwọn igun kan ṣe ìwọ́de pé kí ààrẹ ilé aṣòfin àgbà, Godswill Akpabio kọ̀wé fipò sílẹ̀ lorí ẹ̀sùn iyọnilẹnu fun ibalopọ tí Sẹ́nẹ́tọ̀ Natasha Akpoti fi kàn-án

Igun keji wa n kọ?

Tete lọ sori Ikanni BBC Yoruba fun ẹkunrẹrẹ

''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''

Ayanmọ o gboogun ori lẹlẹjọ

Hmmm, ki lo ri o

Gomina ipinle Oyo, Seyi Makinde, ti da Ọba Samuel Adebayo Adegbola, Eleruwa ti Eruwa ti wọn yọ nipo ọba lọdun 2019 pada si ori itẹ naa bayii

Ki ni yoo wa ṣẹlẹ si idajọ ile ẹjọ to ga julọ to yọ ọ nipo?

Alaye wa lori BBC.Com/Yoruba

''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''

Ọmọ Naijiria, ẹ kaabọ lati Amẹrika

Minisita fọrọ ilẹ okeere Yusuf Tuggar ti sọ fun BBC pe

O tipẹ ti ijọba ti n foju sọna fun ipadabọ awọn ọmọ Naijiria ti ko niwe igbeluu l'Amerika

O ni ijọba ti ṣeto silẹ fawọn ọmọ Naijiria yii ṣaaju ki wọn to de