Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́
Ọga agba ileeṣẹ ologun orilẹede Naijiria, Ọgagun agba Christopher Musa ti tẹnu mọ ọ pe ko si aṣiṣe ninu awọn ado oloro ti baluu ologun ju si ibuba awọn ẹgbẹ agbesumọmi Lakurawa ni ilu Sokoto lọjọru.
Baluu ogun kan ju ado oloro si ileto meji kan ni ijọba ibilẹ Silame ni ipinlẹ Sokoto, eyi to ṣe iku pa awọn eeyan ti ko din ni mẹwaa, ti ọpọ miran si tun ṣeṣe.
Ijọba ipinlẹ Sokoto ti sọ pe awọn eeyan mẹwaa ti ko mọwọ mẹsẹ ninu ọrọ ẹgbẹ agbesunmọmi naa ni wọn ṣekupa lasiko ikọlu ọhun.
Gẹgẹ bi iṣe wọn lọdọọdun, awọn ọmọ ijọ mimọ CCC Sẹlẹ peju pesẹ sibi adura eti okun ti ọdun 2024 leti okun Seme Podji lorilẹede Benin Republic.
Aisun ọjọ Keresimesi ọjọ kẹrinlelogun oṣu Kejila ọdun 2024 ni eto naa gberasọ.
Eto yii tẹsiwaju ni ọjọ kẹẹdọgbọn to jẹ ọjọ ọdun Keresimesi gan an.
Ọpọlọpọ awọn aṣoju ijọ CCC kaakiri agbaye lo wa nibi eto akanṣe adura tọdun 2024 yii pẹlu oniruuru ẹri lati ẹnu awọn ọmọ ijọ to wa nibi eto naa.
Lati ọjọ kẹrinlelogun si ọjọ kẹẹdọgbọn ni ero ti pọ niluu Cotonou ati Seme Kpodji to si dabi ẹni pe wọn fẹ goke Arafat nibẹ nitori eto akanṣe adura eti okun yii ti ọdun 2024 yii.
Prophet Israel Oladele: Àwọn ìlúmọ̀ọ́ka tó ti jọ́sìn ní ijọ CCC, Genesis Global rèé
Àwọn ọ̀dọ́ dáná sun ìjọ CCC lẹ́yìn tí alágbàṣe jábọ́ sínú sọ́kàwee l'Eko


