You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Ìwé ‘Things Fall Apart’ pé ọgọ́ta ọdún
Ìwé ‘Things Fall Apart’ tí Chinua Achebe kọ jẹ́ ìdánwò fún àsà àwùjọ ilẹ̀ Adúláwọ̀ gẹ́gẹ́ bó se ń wáyé lásìkò ìjọba amúnisìn.
Ọdún 1958 ni wọ́n kọ́kọ́ tẹ ìwé náà jáde, tí wọ́n sì ti tú ìwé náà sí àádọ́ta èdè jákèjádò àgbáyé.
Wọ́n ti ta mílíọ́nù méjìlá ìwé náà lágbàáyé.
Lọ́nà áti sàmì ayẹyẹ ọgọ́ta ọdún tí wọn kó ìwé náà síta, ló mú kí àwọn òsèré tíátà nílẹ̀ adúláwọ̀, àwọn òǹkọ̀wé àtàwọn aronújinlẹ̀ se péjọ pọ̀ fún ètò kíka gbogbo ìwé náà lójú táyé.
Ibùdó London South Centre sì ni ètò náà ti wáyé.
Akọ̀ròyìn BBC, Kim Chakanesta náà kò gbẹ́yìn níbẹ̀, tó sì fi ọ̀rọ̀ wá àwọn èèyàn tó wà níbẹ̀ lẹ́nu wò nípa èrò wọn lórí ìwé Things Fall Apart.
Ẹ gbọ ẹ̀dà ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò náà tó se fún Adesua Etomi, tíí se ìlúmọ̀ọ́ká òsèré tíátá àti gbajúgbaja òǹkọ̀wé nnì, Chibundi Onusọ.