Olawale Adeniji Ige: Mínísítà fún ètò ìròyìn tẹ́lẹ̀rí ní Nàìjíríà dágbére fún ayé lẹ́ni ọdún mẹ́rìndínláàdọ́rùn ún

Minisita naa to jẹ agba ninu ijọ Onitẹbọmi Baptist fi ọmọ mẹrin silẹ si aye lọ.

Minisita fun ọrọ iroyin tẹlẹri ni Naijiria, Olawale Adeniji Ige ti jade laye ni ẹni ọdun mẹtalelọgọrin.

Ninu atẹjade ti awọn ẹbi fi lede gba ọwọ ọmọbinrin minisita naa, Atinuke Olashore ni wọn ti kede pe Ọjọ Kẹsan an, Oṣu Karun un ni minisita naa jade laye.

Oloogbe naa ni adari ileeṣẹ ijọba to n risi ọrọ iroyin, ki o to da minisita ẹka naa ni ọdun 1990.

Ni ọdun 1992 ni wọn tun yan an lati ṣakoso ẹka irinna ọkọ ofurufu ati eto iroyin.

Tani Olawale Adeniji Ige to papoda?

Ọjọ Kẹtala, Oṣu Kẹwaa, ọdun 1938 ni wọn bii ni Ilu Eko, amọ ọmọ bibi Ile Seedu, Ijeru ni Ogbomosho, nipinlẹ Ọyọ ni.

To si bẹrẹ iṣẹ pẹlu ileeṣẹ iroyin Nigerian Broadcasting Corporation gẹgẹ bi amoju ẹrọ ni ọdun 1957.

Lẹyin naa lo tẹ ọkọ leti lọ si oke okun lati lọ kọ imọ Electrical Engineering si ni ọdun 1961.

Lẹyin to pada si Nigeria ni 1967 ni o bẹrẹ iṣẹ pẹlu ileeṣẹ ijọba apapọ to n risi eto iroyin ati ibanisọrọ ni Naijiria titi ti o fi di ọga patapata ni ọdun 1985.

Minisita naa to jẹ ara ijọ Baptist fi ọmọ mẹrin silẹ si aye lọ.