You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Niger kidnap: Mẹ́fà nínú àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ilé ẹ̀kọ́ Islamiyya Tegina ti kú sí àkàtà àwọn ajínigbé
Mẹfa ninu mẹrindinlogoje akẹkọọ ile ẹkọ Salihu Tanko Islamiyya tawọn janduku ajinigbe pawo jigbe niluu Tegina nipinlẹ Niger ti ku si akata awọn ajinigbe.
Ọga ile ẹkọ naa, Abubakar Alhassan, ṣalaye pe lana ọjọ Iṣẹgun lawọn janduku ọhun sọrọ iku awọn akẹkọọ naa foun lori foonu.
Awọn ajinigbe ni aisan ajeji kan lo ṣekupa awọn ọmọ naa ninu igbo ti wọn wa.
- Bí àwọn jàndùkú ṣe kọlu ilé ẹ̀kọ́ ẹ̀kọ́ṣẹ́ ọmọogun Nàìjíríà (NDA)
- Adájọ́ pàṣẹ ìtúsílẹ̀ mẹ́rin lára ọmọlẹ́yìn Igboho 12 tó wà ní àhámọ́ DSS l'Abuja
- Wo ìgbà mẹ́ta tí Olusegun Obasanjo ti fi ìdọ̀bálẹ̀ nàá fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ níwájú àwọn oríadé
- Àwọn jàndùkú afẹ̀mí-ṣòfò ṣekúpa èèyàn 24 ní Kaduna àti Katsina lọ́jọ́ kan ṣoṣo
- Tètè wá gbé òkú eèyàn rẹ bí bẹ́ẹ̀ kọ́ a ó sìn wọ́n papọ̀ mọ́ tí 200 lópin ọ̀sẹ̀- Iléeṣẹ́ Ọlọ́pàá
- Kò sí bí wọ́n á ṣe máa ka ọta ìbọn fún Sọ́jà tí a maa lè borí Boko Haram- Olagunsoye Oyinlola
- Ọlọ́run nìkan ló lè ní kí Tinubu má jẹ ààrẹ lọdún 2023, ìmọ̀ràn lọ̀rọ̀ Yahaya Bello- Joe Igbokwe
Awọn janduku ajinigbe yii si duro lori ẹsẹ wọn pe igba miliọnu naira lowo itusilẹ tawọn n beere fun lawọn si maa gba, bo tilẹ jẹ pe mẹfa ti ku ninu awọn akẹkọọ naa bayii.
Abubakar Adam, ọkan lara awọn obi to ni ọmọ mẹfa lakata awọn ajinigbe naa fidi ọrọ ọhun mulẹ.
Iroyin kan tiẹ sọ pe awọn obi pakiti mọri wa aadọta miliọnu san fawọn janduku ọhun, ṣugbọn wọn ni igba miliọnu gbọdọ pe.
Awọn eeyan awujọ Alawa ni ijọba ibilẹ Shiroro nipinlẹ Niger State ti sọ tẹlẹ pe awọn ri awọn akẹkọọ ọhun nibi ti wọn ti n gbe wọn lọ lori ọkada.
Amọ, ko si ẹni to tii gburo wọn di akoko yii.
Ẹwẹ, kọmiṣọnaa ọlọpaa tuntun nipinlẹ Niger, Bala Kuryas ti sọ pe ile iṣẹ ọlọpaa yoo wa awọn ọmọ ri laipẹ.
Iṣẹlẹ ijinigbe ti ṣẹlẹ lera lera ni ipinlẹ Niger, awọn akẹkọọ lo si pọju ninu awọn ti wọn jigbe.
- Ọlọ́run nìkan ló lè ní kí Tinubu má jẹ ààrẹ lọdún 2023, ìmọ̀ràn lọ̀rọ̀ Yahaya Bello- Joe Igbokwe
- Aya adarí ìjọba ológun Naijiria tẹ́lẹ̀rí, Victoria Aguiyi-Ironsi ti jáde láyé
- Wo ìgbà mẹ́ta tí Olusegun Obasanjo ti fi ìdọ̀bálẹ̀ nàá fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ níwájú àwọn oríadé
- Secondus, alága PDP ní òun kò bẹ̀rù àṣẹ ilé ẹjọ́, kí ẹgbẹ́ má bàjẹ́ ni tòun
- Akọ̀wé APC, èèyàn mẹ́fà míràn fojú ba ilé ẹjọ́ fún fífọ́ òkúta mọ́ ọmọ ẹgbẹ́ lórí l' Ọ̀ṣun
- Mi ò bínú sí gbogbo nǹkan ti Chioma sọ nípa mi- Apostle Suleiman