Coronavirus in Nigeria: Ọmọ Nàìjíríà 292 láti Saudi Arabia gúnlẹ̀ sí Abuja

Baluu kan n balẹ

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

Ọdunrun o din mẹjọ lawọn ọmọ orilẹede Naijiria to gunlẹ si ilu Abuja lati orilẹede Saudi Arabia lalẹ ọjọ Iṣẹgun.

Minisita fọrọ ilẹ okeere lorilẹede Naijiria, Geoffrey Onyeama lo fi idi ọrọ yii mulẹ loju opo twitter rẹ lọjọru.

O ni pupọ lara awọn ọmọ orilẹede Naijiria ti wọn ko wale naa ni wọn jẹ obinrin to n tọ ọmọ lọwọ atawọn ọmọde. O fi kun un pe wọn ti fi wọn si ipamọ lawọn ileetura labẹ amojuto ajọ to n dena ajakalẹ arun lorilẹede Naijiria, NCDC.

Skip X post, 1
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 1

Minisita Geoffery Onyeama ṣalaye pe ijọba orilẹede Saudi Arabia lo ṣe atọna bi awọn eeyan naa ṣe de orilẹede Naijiria.

Bakan naa lo sọrọ lori awọn ọmọ Naijiria kan to n kẹkọ lorilẹede Malaysia to si ni ijọba apapọ ko tii gbọ iroyin pe wọn fẹ le awọn akẹkọ naa nitori pe iye ọjọ to wa lori iwe igbelu wọn ti pe.

Awọn kan lo kan si ileeṣẹ ọrọ ilẹ okeere lorilẹede Naijiria pe ẹgbẹrun mẹtala lawọn ọmọ orilẹede Naijiria to n kẹkọ ni Malaysia, ṣugbọn ti o ṣeeṣe ki ijọba orilẹede naa o fi tipatipa da pada sile nitori iye ọjọ to wa lori iwe igbelu wọn ti ko.

Skip X post, 2
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 2