Aminat Abọdun: Ọ̀pọ̀ èèyàn se ẹ̀yẹ ìkẹyìn fún akọni obìnrin tó lọ
Ọjọ manigbagbe ni ọjọ Aiku nilẹ Ibadan nigba ti wọn fi tiyi-tẹyẹ ki Iyalode ilẹ Ibadan, Oloye Aminat Abiọdun pe o digbose.
Nigba to n ba BBC Yoruba sọrọ, Oloye Lekan Alabi ni Iyalode Abiọdun jẹ onisowo lati kekere, to si ri ja jẹ.
Lero ti Agba Amofin Adeniyi Akintọla, "General lo yẹ ka maa pe Aminat Abiọdun, ko se fi ọwọ rọ sẹyin lawujọ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ìbejì Oníbẹ̀mbẹ́ Òru tí kò yara wọn lẹ́yìn ọgọ́ta ọdún
- Ohùn ìjálá lásán ni mo fi ń pa ẹran nínú igbó - Ọdẹ Oníjàálá
- Mo fẹ́ ọkọ mi torí bó se ń kọrin, kìí se torí owó - Ìyàwó Aràrá
- Mo fẹ́ kí àyẹyẹ ìgbeyàwó mi dùn ni mo se bú sẹ́kún - Ọkọ ìyàwó ẹlẹ́kún
- Samuel Ladoke Akintọla jẹ́ Agbẹjọ́rò àti Akọ̀ròyìn tí ọ̀rọ̀ dá lẹ́nu rẹ̀
- Hubert Ogunde rèé, baba àwọn òsèré tíátà
- Ìyàtọ̀ wà nínú ìlépa àwọn òṣèré tíátà ayé àtijọ́ àti ìsisìnyí-Papalolo
O mọ oge se, kii jẹ ounjẹ iwọsi, ko si si ẹni ti ko lee wo oju rẹ.
Awọn ọmọ ati ọmọ oloogbe to ba wa sọrọ ni, Iyalode to di oloogbe naa ni aajo ọmọ, o nibẹru Ọlọrun, ti ko si si isoro ti ko lee ba eeyan yanju rẹ.
Ọpọ eekan ilu nilẹ Ibadan, nipinlẹ Ọyọ ati nilẹ Yoruba lo peju sibi ẹyẹ ikẹyin ti wọn se fun Oloye Aminat Abiọdun.