Fayoṣe: Iná tí kò ní pẹ̀ ẹ́ kú ni àṣeyọrí Fayẹmi

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Gómìnà ìpìnlẹ̀ Èkìtì,ti ní kí Kayọde Fayẹmi maa tì i dun nú fún bó ṣe borí nínú ìdìbò abẹ́lé APC.
Ayọdele Fayoṣe, tó sọ̀rọ̀ nàá nínú ìkéde kan tó fi síta lójú òpó Twitter rẹ̀ ní ''iná tí yòó kú lọ́ja kẹrìnlá, oṣù Keje ní àṣeyọrí Fayẹmi.
Ó ní ''kí Fayẹmi ní ìrètí wí pé ìjákulẹ̀ rẹ̀ nínú ètò ìdìbò tó n bọ̀ yóò burú fun un ju ti 2014."
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Fayẹmi tó jẹ́ mínísítà fún ìdàgbàsókè ìwakùsà àti ìrìn rírọ́ ló gbégbá orókè nínú ètò ìdìbò abẹ́lé ẹgbẹ́ All Progressives Congress, tó wáyé lọ́jọ́ Àbámẹ́ta láti yan ẹni tí yóò ṣojú ẹgbẹ́ nàá nínú ètò ìdìbò sí ipò gómínà tí yòó wáyé lọ́jọ́ kẹ̀rìnlá, oṣù Keje, 2018.








