You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Rauf Aregbesola sọ bó ṣe yẹ kí òbí máa fètò sọ́mọ bíbí
Minisita to n ri si ọrọ abẹle lorilede Naijiria to tun jẹ gomina ana ipinlẹ Osun, Ọgbẹni Rauf Aregbesola ti ni ki awọn obi din iye ọmọ ti wọn n bi ku.
Aregbesola sọ eyi gẹgẹ bi ọkan lara awọn koko ọrọ to maa n fi sita lori ayelujara.
O fi ọrọ rẹ gba awọn lọkọ-laya nimọran lati fi eto si bi wọn ṣe n bimọ nitori ipo ti orlẹede Naijiria wa lọwọlọwọ.
Loju opo Twitter ti Ọgbẹni Aregbesola maa n lo fi kọ awọn koko ọrọ kekeke, o ni "a rọ awọn lọkọ-laya lati maa feto sọmọ bibi".
Bí mo bá ṣáájú ìwọ́de ENDSAReS, kẹ́ẹ mọ̀ pé ẹ̀wọ̀n Kirikiri ni wọ́n á gbé mi lọ jàntò - Naira Marley
O tẹnu mọ ọ pe "a ti n bimọ ju iye awọn ti orilẹede ṣetọju lọ. Torinaa, ọmọ meji si mẹta ti to".
Aregbe ni o yẹ keeyan ṣe bo ṣe mọ ni, ẹlẹwa sapọn lori ọrọ ọmọ bibi lorilẹede Naijiria.
Niwọnba iwọn iye owo tabi na atijẹ ti eeyan ni ni Ọgbẹni Aregbesola ni o yẹ keeyan wo ko to maa ka ọmọ jọ.