You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Àwọn agbébọn jí alága ẹgbẹ́ òsèlú PDP gbé ní Kogi
Àwọn agbebon tí wón wo aṣọ ọmọ iṣẹ́ ológun ni a gbọ́ pé, wón ti jí alága ẹgbẹ́ òṣèlú PDP tí ìjọba ìbílè Okene, Ogbeni Musa Adelabu, gbé lọ ni dédé agogo kan òru ọjọ́ ìsimi.Nígbà tí ó ń fi ọ̀rọ̀ náà lédè, alága ẹgbẹ́ òṣèlú náà ni ìpínlè Kogi, Sam Uhuotu, sọ wí pé, Ìpínlẹ̀ Kogi, tí di ẹru jeje fún olùgbé ìpínlè náà.
Ó te siwaju pé, àwọn agbebon náà wo aṣọ ológun nígbà tí ṣe akọlù sí ilé ẹ rè ni dédé aago kan òru ọjọ́ ìsimiÓ fi kun pé, akọlù sí ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú PDP ní ìpínlè náà fẹ́ àbójútó látàrí bíi àwọn agbebon tí wón ń wọṣọ ológun láti ṣe irú ìṣe láabi náà ń wọ́pọ̀ sii.Uhuotu ṣàlàyé wí pé, títí di àsìkò tí a ń sọ̀rọ̀ yìí, kò sí eni tí ó mọ, ibi tí alága náà wọlé sí.Àmọ́ ṣáá o, alukoro àjọ olopaa ní ìpínlè náà, Williams Aya, sọ wí pé, kò tí ì sí eni tí ó mú ẹ̀sùn íjini gbé bẹ́ẹ̀ tó wọn létí.