Bàálù to gbe Yemi Oṣinbajo já lulẹ̀ ní Kogi

Oríṣun àwòrán, LAOLU AKANDE
Iroyin to n tẹwa lọwọ ni pe ọkọ baalu Igbakeji Aarẹ Naijiria, Yẹmi Ọṣinbajo ja lulẹ ni ilu Kabba nipinlẹ Kogi laipẹ yii.
Amugbalẹgbẹ rẹ, Laolu Akande lo fi ikede naa sita loju opo Twitter rẹ.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
A gbọ wipe lasiko ti baalu ayarabiaṣa naa fẹ ẹ ba lo ja lojiji. Ṣugbọn Ọṣinbajo ati awọn ti wọn jọ wa ninu baalu naa ko ni ifarapa kankan.
Ko pẹ ti ijamba naa waye ni Ọṣinbajo fi fidio kekere kan soju opo Instagram rẹ. O sọ ninu ọrọ rẹ pe ''Gbogbo ogo fun Ọlọrun, baalu ayarabiaṣa to gbe wa lati ilu Abuja ja lulẹ nigba to fẹ ẹ ba silẹ nilu Kabba, nipinlẹ Kogi.
Emi ati awọn ti a jọ wa ninu rẹ wa ni alaafia, a si n tẹsiwaju ninu eto 'Next level' wa ati ipinnu wa fun ipinlẹ Kogi."
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post








