Testimony Jaga sọ ohun tójú rẹ rí kó tó lè wo ara rẹ̀ láwòdúpẹ́

"Kí n máa kọrin Ọlọ́run láàrín àwọn amugbó pé mi ju kí wọ́n pè mí sí ìsọjí ńla lọ".

BBc Yoruba ba akọrin ẹ́mi ti ọpọlọpọ mọ si Testimony Jaga lalejo nile orin rẹ.

Jaga kẹnu bọrọ, ko fẹ tan mọ tori itan igbesi aye rẹ ko to de ibi to yanju fọwọ tọ ni lọkan gan.

"Ìdíle olórógún lórí mi yàn nígbà tí mo dé ayé. Ìyawó mẹ́fa, àwa ọmọ 27, láàrín wọn ni mo ti jáde".

Jaga ni ipo kejilelogun loun wa ninu awọn ọmọ baba oun. O ni "ìyá mi kò rí mi bí lásìkò tó yẹ kí ó bi mi, Ọ̀tá mi tún kú lọ́jọ́ ìkómọ fún wákàtí mẹ́jọ".

"Mo ti kó sọ́wọ́ Ọlọ́pàá lọ́pọ̀ ìgbà, SARS, Area G ...iya mi nikan lo maa n wa lẹyin mi ni gbogbo igba titi ti Ọlọrun fi ṣeyanu ko to di pe awọn oniroyin gbe mi saye".

Ohun ti Jaga la kọja lo jẹ ko sọ fun Ọlọrun pe bi o ba le ko oun yọ ninu iṣoro, oun a sin in.