You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Corona Virus: Àyẹwò fi han pé kìí ṣe àìsàn naa lo ń se àkẹkọọ ti wọ́n fura si
Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1
Nínú ìbẹ̀rù bojo àti ìfòyà ni ọ̀pọ̀ ọmọ Naijiria wá lẹ́yìn ti ìròyìn tà kan pé, óṣeeṣ ki àìsàn náà ti wọle si orilẹ̀-èdè Ivory Coast èyi to jẹ ilẹ adúlawọ.
Sùgbọ́n ìdùnú subu lú ayọ fun gbogbo ènìyàn ilẹ Afirika wi pé àbájade àwọn àyẹwò ti wọ́n ṣe fun àkẹkọ̀ọ́ náà fi han pe ko ni àìsàn náà.
Iroyin to fi ìdí ọ̀rọ̀ náà múlẹ̀ wáye nínú àtẹjáde kan ti ile iṣẹ́ ètò iléra orílẹ̀-èdè náà gbé jáde ti wọ́n si fi si lóri àtẹjisẹ Facebook
Kokoko lára akẹkọ̀ọ́ náà le ti o sì ti padà si ọ̀dọ̀ àwọn ẹbi rẹ̀.