Akinwumi Ambode: Awọn àgbà ọ̀jẹ̀ agbábọ̀ọ̀lù ní Afíríkà yẹ́ Gomina Ambode si

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

Ọ̀pọ̀ àwọn àgbà sjẹ̀ oníbọọ̀lù láti orilẹ̀-èdè Nàìjíríà àti Afíríkà ló péju sí pápá ìṣere Agege lọ́nìí láti yẹ gọmina ìpínll Eko Akinwumi Ambode bí ó ṣé ń fi ìpò sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bii gómìnà.

Awọn ènìyàn bi George Weah to jẹ ààrẹ orilẹ̀-èdè Liberia, Eto'o, Toure lo yẹ ko peju sibi ayẹyẹ ohun.

Nínú ọ̀rọ̀ ìdúpẹ̀ rẹ̀ gómìnà Akinwumi Ambode ni inú òhun dùn gidigidi bí àwọn agbábọ̀ọ̀lù náà ṣe ṣe àyẹ́sí fún òhún, o ni àwọn dájọ, ọjọ́ náà sikò àti pe òun dupẹ lọ́wọ́ àwọn to ṣe àgbátẹrùn ètò náà àti gbogbo àwọn to wá si pápá ìṣèré náà láti wa wòran

Awọn olólùfẹ́ gómìnà Akinwumi Ambode náà ko gbéyin lóri àtẹjiṣẹ́ twitter láti fi ìdùnú wọn han lórí ìfẹsẹwọnsẹ náà.