You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Nigeria Elections 2019: Àwọn ọmọ Nàìjíríà n ṣé hèèmọ̀ bí INEC ṣé dajọ sí ibo
Kini ka ti ṣe eyi si?
Ọrọ ti o gba ẹnu ọpọ ọmọ Naijiria ree lẹyin ti ajọ eleto idibo orile-ede Naijiria da ọjọ si idibo Aarẹ ati ti awọn aṣoju ile aṣofin ti o yẹ ki o waye lọjọ Abamẹta.
Ọrọ naa ṣe ọpọ ni kayefi lataari pe ajọ naa ko tawọn lolobo pe irufẹ iṣẹlẹ bayi yoo waye.
Loju opo Twitter iyalẹnu ni o kọkọ bẹrẹ iriwisi awọn ọmọ Naijiria nigba ti iroyin naa wọ wọn lara tan, ṣeni ọpọ bẹnu ẹ̀tẹ́ lu INEC
Ikanra lawọn miran fi n fẹsi si ikede yi.
Ogbeni Dipo yatọ si pe o gba adura fun itusilẹ Naijira faraya pe awọn ọmọ orile-ede kan rin irinajo wakati marun un lati le lọ dibo eleyi ti ko waye mọ
Iha miran lọrọ yi kọ si ẹlomiran bi Naturalguy4eva ti o n kaanu awọn ti wọn ti dajọ igbeyawo si ọjọ kẹtalelogun Osu keji ti Inec sun idibo naa si