You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Nigeria Election 2019:Awọn wò ní Gómìnà El Rufai n ba wi pẹlu ihalẹ 'body bag'
'Onwoye kankan lati ilu okere to ba n bọ lati dasi idibo Naijiria ko ni fara re pada sile.'
Ikilọ yi ti a pẹ sọ nitori bi o ti ṣẹ lagbara to ni Gomina ipinlẹ Kaduna lorileede Naijiria Ahmad El Rufai fi sita eyi to si ti n da awuyewuye silẹ
Lori eto kan to waye nileeṣẹ amohunmaworan Naijiria ni Gomina El Rufai ti sọ ọrọ yi lalẹ ọjọ iṣẹgun.
Eyi kii ṣe igba akọkọ ti El Rufai yoo ma sọ ọrọ to n da wahala silẹ.
Lai pẹ yi ni awuyewuye waye lori bi o ti ṣe juwe olori ẹgbẹ ẹsin Shia Zakzakky gẹgẹ bi ẹrankọ ninu ifọrọwerọ kan lori ẹrọ amohunmaworan
Ninu awọn to ti n faraya lori ọrọ naa lati ri Femi Fani Kayode,Aisha Yesufu ati Sẹnẹtọ Ben Murray Bruce to fi mọ ẹgbẹ oselu PDP ti wọn bu ẹnu atẹ lu ihalẹ El Rufai yi.
Ẹgbẹ PDP ni awọn ko ni igbagbọ pe pẹlu iru ọrọ to n jade lẹnu El Rufaiu yi,awọn yoo ni lati se agbeyẹwo iwe adehun idibo alafia ti awọn buwọlu.
Kiakia ni akọwe ipolongo ẹgbẹ naa ti fi ọrọ sita loju opo Twitter nipa ọrọ yi.
Amọṣa Gomina El Rufai ti salayeidi ti o fi sọ ọrọ naa loju opo Twitter rẹ ni idahun si iriwisi orisirisi to muwa.