NLC: Àwọn olósèlú ń la títì láì sanwó osù torí owó tí wọn yóò rí lórí àkànse isẹ́
Iyansẹlodi awọn osisẹ ijọba lẹlẹkajẹka n wáyé ni orilẹ-ede Naijiria nitori owo osu to kere pupọ ti wọn ni ijọba n san fawọn.
BBC Yoruba wa bọ sigboro lati mọ ohun tawọn osisẹ yii ri lọbẹ, ti wọn se wa iru sọwọ. Ọpọ wọn to ba wa sọrọ ni iya awọn osisẹ ni Naijiria ti pọ ju.
Wọn ni awọn osìsẹ́ Nàíjíríà wà lóórùn, náwónáwó àwọn olósèlú wà ní bòòji, ti wọn ko si naani eto idẹrun awọn osisẹ.