Fashola: Omi ń bẹ lámù nídìí ìpèsè ina ọba

Oríṣun àwòrán, Reuters
Ibùdọ Amúnáwá ní Nàìjíríà tún ti kọsẹ́ lẹ́ẹ̀mejì láàrín ọjọ́ márùn ùn, bẹ́ẹ̀ iná ọ́ba ti ń se déédéé láti bíi osù méjì sẹ́yìn ní orílẹ̀èdè Nàìjíríà.
Ìròyìn fihàn pé ó ti sẹlẹ̀ lẹ́ẹ̀mẹfà níbẹ̀rẹ̀ ọdún 2018.
Báwo ló se sẹlẹ̀
Àkọsílẹ̀ láti ilé isẹ́ ìjọba àpapọ̀ tó ń rísí ọ̀rọ̀ isẹ́ òde, iná mọ̀nàmọ̀nà àti ilégbèé nílu Àbújà fihàn pé, Ibùdọ Amúnáwá da isẹ́ sílẹ̀ láàrín ọjọ́ kejìlá sí ọjọ́ kẹrìnlá, osù kẹrin ọdún yìí, èyí tó sì ń dààmú ìpèsè iná títí di ìsinyìí.
Ọjọ́ kínní osù kejì ló kọ́kọ́ sẹlẹ̀ lọ́dún yìí kó tó tún dákú padà báyìí.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí

Ogbẹ́ni Usman Mohammed to je olùdarí ẹ̀ka tó ń pín iná mọ̀nàmọ̀nà ní Nàìjíríà wá pè fún àtúnse sí àwọn ohun eèlò tí wọn ń lò fi n mú iná wá pẹ̀lú àjọsepọ̀ àwọn olókoòwò ńlánlá láti ilẹ̀ òkèèrè.
Fasola gbà pé ìdàgbàsókè iná mọ̀nàmọ̀nà jẹ ìjọba lógún fún ilọsíwájú ètò ọrọ̀ ajé Nàìjíríà pàápàá lásìkò yìí.









