Libya Returnee: Odindi ọjọ́ kan ni mo fi wà ní ìhòhò ní Libya tí gbogbo èrò n fi ọwọ́ pa mí lára- Adenike Abode Libya

Adenike Olanipekun, ọkan lara awọn abọde Libya ti wọn n fi iriri wọn kọ ọpọ ọdọ Naijiria lẹkọọ sọrọ ilẹ kun.

O salaye gbogbo nkan ti oju rẹ ri lati igba to ti kuro ni Naijiria to fi de Ghana to tun fi de Libya.

Emi ati Iya mi ta gbogbo nkan ini wa ki n le ri owo mu lọ si Libya ṣugbọn ibanujẹ ni mo mu bọ lairi kọbọ kan fi ran ile lọwọ.

Adenike Olanipekun salaye pe awọn aadọta ni wọn n sun sinu iyara kan ṣoṣo.

Koda, o ni pe lati oju ọna ni awọn ọlọpaa ti n mu wọn ba sun lọkọọkan.

O ni Ibrahim aisha ni orukọ tuntun ti wọn fun oun nibẹ.

O sọ nipa ifipabanilopọ ti oju rẹ ri.

Adenikẹ gba awọn ọdọ Naijiria ni imọran, o tun ranṣẹ si ijọba Naijiria lori ọrọ irinajo tipatipa lo silẹ okeere to wọpọ laisko yii.

O ni ẹgbẹrun marun un naira ni ijóba pin fun wọn lati fi lọ bẹrẹ iṣẹ lẹyin to de pada sile.