Àwọn olùdìbò sọ òkò pa ọkùnrin kan tí wọn ló da ìbò rú
Lónìí, ọjọ́ kẹtà oṣù kejì ọdún 2019 ni ìdìbò tí àjọ elétòìdìbò, INEC sún síwájú fún ààrẹ àti ilé aṣofin àgbà.
Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tí ń lọ lọ́wọ́
Yetunde Olugbenga
Ìyá àgbà rin kìlómítà méjì láti dìbò

Oríṣun àwòrán, @CaptainArinze
Iya agba kan ree to rin irin kilomita meji lati lọ dibo loni.
Iya agba naa, to le ni ọgọta ọdun, lo ti fẹyinti lọdun meji sẹyin.
Iya agba ọhun lo gbe ẹni lọwọ lọ si agọ idibo, ni kete to de ibẹ si lo sun lori ẹni ki ibo to kan.
Ọmọ iya naa, to gbe aworan rẹ soju opo Twitter ni, iya agba naa fẹ sa ipa rẹ ni, lati jẹ ki orilẹ ede yii dara fawọn ọmọ ọmọ rẹ lọjọ ọla.
Àwọn olùdìbò sọ òkò pa ọkùnrin kan tí wọn ló da ìbò rú

Iroyin to n tẹ wa lọwọ ni pe, pẹlu ibinu ni awọn oludibo fi sọ oko pa ọ̀kunrin kan ti wọn lo da ibo ru, ni adugbo Okota, Ago Palace Way, Isolo nilu Eko.
��uP�
Ẹgbẹ òṣelu Fayose PDP bori ni agọ idibo rẹ
(82).

Àkọlé àwòrán, Ayo Fayose Ayọdele Fayose, tii se gomina ana nipinlẹ Ekiti, to tun jẹ ogbontagi ẹgbẹ oselu PDP, ti jawe olubori ninu agọ idibo rẹ.
Ni agọ̀ idibo naa ni pDP ti ni ibookolerugba ati marun, (225) nigba ti ẹgbẹ oselu APC, ni ibo mejilelogojib
APC mókè ní àgọ́ ìdìbò Akeredolu

Ẹkọ ko se oju mumu fun ẹgbẹ oselu PDP ni agọ idibo ti Gomina Rotimi Akeredolu ti dibo nipinlẹ Ondo.
Ìbò kíkà bẹ̀rẹ̀ ní Ẹdẹ


Ibo kika ti bẹrẹ ni agọ idibo kẹsan to wa ladugbo Abegunde/Sagba, nijọba ibilẹ Ariwa ati Guusu Ede, nipinlẹ Osun.
Agọ idibo yii ni Senetọ Ademola Adeleke ti dibo.
Àwòrán àwọn ìwé ìdìbò tí wọn jó níná

Jàǹdùkú dáná ṣun àpótí ìbò l‘Eko
Àkọlé fídíò, Olùdìbò Eko: Irú orílẹ̀èdè wo lèyìí? Ìná sọ lórí àpòtí ìbò, 'irú orílẹ̀èdè wo lèyìí?'
Awọn oludibo agbegbe Isolo ni ilu Eko sọ iriri wọn nibi ti wọn ti n jo apoti ibo nina.
Ọ̀gá ọlọ́pàá Eko kàn sí Ọkọta tí wàhálà ti ń wáyé

Idi isẹ ẹni laa ti mọni ni ọlẹ.
Idi ree ti ọga ọlọpa nipinlẹ Eko fi kan si adugbo Agọ palace, ladugbo Ọkọta, nipinlẹ Eko, lati pẹtu si aawọ to n waye ni agọ idibo kan nibẹ.
Àwọn ọ̀dọ́ ni wọ́n rán láti lé olùdìbò PDP kúrò l‘Eko - Olùdìbò
Àkọlé fídíò, Raph Nwadike ni awọn ọ̀dọ́ tí kò tó ọgbọ̀n ọdún, ló ń ṣá wa lọ́gbẹ́ ni Eko. Ọ̀rọ̀ di bóò lọ, ko yà fún mi ní Ọkọ́ta, nílùú Eko



Awọn janduku tun da ibo ru ni adugbo Agọ Palace nilu Eko.
Wọn dana sun ọkada kan, ti awọn osisẹ ajọ eleto idibo si fẹsẹ fẹ.
Lawọn oludibo ba se ọrọ naa ni ẹniti ori yọ, o di ile.
Ọkùnrin kan ń ta igbó ní àgọ́ ìdìbò

Awọn osisẹ alaabo pajawiri lo gba ọkunrin yii mu lasiko to n polowo igbo tantan tan ladugbo Berger nilu Eko.
Awọn agbofinro RSS ti gba mu, ti wọn si ti fa le agọ ọlọpa Base 105, to wa ladugbo Ojodu lọwọ.
Sanwo-Olu náà ti dìbò

Àwọn jàǹdùkú fín wa lẹ́gba pé APC nìkan ni ká máa tẹ̀ka fún l‘Eko - Olùdìbò
Àkọlé fídíò, Àwọn olùdìbò ìpínlẹ̀ Eko sọ ìrírí wọn Ìbò kíkà bẹ̀rẹ̀ ní Ilọrin

Ibo kika ti bẹrẹ ni wọọdu Oke Erin, ile ẹkọ Queens school keji, nilu Ilọrin.
Aago meji ọsan ni ibo didi pari nibẹ.
Ìyàwó igbákejì ààrẹ wa ọkọ rẹ̀ lọ sí àgọ́ ìdìbò

Hù[, ifẹ́ yii dara pupọ.
Dọlapọ, tii se aya igbakeji aarẹ, ọjọgbọn Yẹmi Ọsinbajo lo wa ọkọ rẹ si agọ idibo, ti awọn mejeeji ti dibo.
Ìbò kíkà bẹ̀rẹ̀ ní Ikẹrẹ Ekiti

Ibo kika tí bere ni pereu ni agọ idibo keje, wọọdu keji nilu Ikẹrẹ Ekiti.
Ọ̀rọ̀ di bóòlọ, ko yà fún mi ní Ikirun



Awọran yii lo n sọ bi awọn janduku kan se da ibo ru ni ilu Ikirun.
Se ni wọn da apoti ibo nu, ti awọn iwe idibo si doju de.
Àsùnfọnfọn ni ti 'fọ́n
Iru oorun wo la le ni arakunrin yi,Yusuf Sani sun ni Kano debi pe wọn pari ibo laaye idibo rẹ ki o to taji?

Oríṣun àwòrán, bb
Àkọlé àwòrán, Aworan oludibo to sun gbagbe idibo Àwọn agbófinró ń gbéra lọ pẹ̀tù sí aáwọ̀ ní Aguda

Awọn agbofinro ti n fi agbara kun agbara wọn ni adugbo Aguda, nipinlẹ Eko.
Adugbo yii ni awọn janduku ti kuna lati da ibo ru bi o tilẹ jẹ pe wọn da wahala silẹ nibẹ.



