Eyi ni opin akojọpọ iroyin ti a ti n mu wa fun yin lori bi awọn asofin Naijiria kan se fi ẹgbẹ oṣelu wọn silẹ l'oni.
A lero pe ẹ gbadun wa?
Ẹ maa gbagbe lati maa kan si bbc.com/yoruba fun iroyin lọlọkan ko j'ọkan ni ede Yoruba.
Ẹ ṣe pupọ.
À n mú ìròyìn wá fún yín lórí bí iléèṣẹ́ ọlọ́pà ṣe dí ẹnu ọ̀nà ilé Bukọla Saraki, àti ìjà tó n wáyé láàrin òun àti ìṣàkóso Muhammadu Buhari
Busayo Akogun
Eyi ni opin akojọpọ iroyin ti a ti n mu wa fun yin lori bi awọn asofin Naijiria kan se fi ẹgbẹ oṣelu wọn silẹ l'oni.
A lero pe ẹ gbadun wa?
Ẹ maa gbagbe lati maa kan si bbc.com/yoruba fun iroyin lọlọkan ko j'ọkan ni ede Yoruba.
Ẹ ṣe pupọ.
Aarẹ ile aṣofin, Bukọla Saraki, ti lewaju awọn aṣofin kan lọ sile igbakeji rẹ, Ike Ekweremadu.
Ṣaaju ni awọn ọlọpa yi ile Ekweremadu ka ni òwúrọ̀ òní.
Ọkan lara awọn oluranlọwọ fun Ekweremadu, sọ fun BBC pe, awọn sẹnetọ ati awọn ọmọ igbimọ amuṣẹya ẹgbẹ oṣelu PDP wa lara ikọ̀ tó tẹlé Saraki lọ sile Ekweremadu.

Gomina ipinlẹ Ekiti ti yoo fi ipo naa silẹ laipẹ, Ayodele Fayose, ti ni opin ko ni i pẹ de ba ijọba to n lo asẹ onikumọ l'orilẹ-ede Naijiria.
O sọ eyi l'oju opo Twitter rẹ l'oni.
Ọrọ naa to sọ wa ni ibamu pẹlu bi awọn sẹnetọ kan ati awọn ọmọ ile aṣofin kekere ni Naijiria ṣe fi ẹgbẹ to wa ni iṣakoso lọwọ-lọwọ, APC, silẹ l'oni.
Fayoṣe jẹ ẹnikan gboogi to maa n tako iṣakoso Aarẹ Muhammadu Buhari.
Ajọ EFCC ti ransẹ si igbakeji aarẹ ile aṣofin agba Naijiria, Ike Ekweremadu, lati wa sọ t'ẹnu rẹ lori awọn iwadi kan ti wọn ni awọn n ṣe lori ẹsun ìgbìmọ̀ ọ̀tẹ̀, àṣìlò ipò, àti jíjí owó ìlú.
Ọkan lara awọn oluranlọwọ fun Saraki, Bamikole Banks Omisore lo fi aworan lẹta kan sita to sọ pe EFCC kọ si Ekweremadu loju opo Twitter rẹ.
Ṣugbọn, BBC ko le sọ boya ojulowo ni lẹta naa tabi ayederu.
Fidio yii n ṣafihan aarẹ ile aṣofin agba Naijiria, Bukọla Saraki, bo ṣe n fi gbọ̀ngàn ilé aṣofin silẹ̀ lẹyin to so ijoko ile to waye l'ọ́jọ́ kẹrinlelogun, oṣu Keje rọ di ọjọ kẹẹdọgbọn, oṣu Kẹsan.
Amugbalẹgbẹ Saraki, Bamikọle Banks Omisore, lo fi fidio naa sita loju opo Twitter rẹ.
Alaga ẹgbẹ oṣelu APC, Adams Oshiomole sọ pe inu oun dun pe awọn sẹnetọ kan to jẹ ọmọ ẹgbẹ́ naa fi ẹgbẹ́ silẹ lọ si PDP.
O sọ bẹ fun awọn akọroyin to wa ni ile aarẹ, lẹyin ipade kan to ṣe pẹlu Aarẹ Muhammadu Buhari l'oni.
O ni 'ẹgbẹ́ oṣelu naa ko ni imọlara bi wọn ṣe fi ẹgbẹ́ silẹ̀, nitori awọn yoo ṣi bori ninu eto idibo 2019.'

Oríṣun àwòrán, NAN
Dino Melaye (Kogi)
Barnabas Gemade (Benue)
Ibrahim Danbaba (Sokoto)
Shaaba Lafiaji (Kwara)
Ubali Shitu (Jigawa)
Rafiu Ibrahim (Kwara)
Suleiman Hunkuyi (Kaduna)
Isa Misau (Bauchi)
Monsurat Sunmonu (Oyo)
Soji Akanbi
Usman Nafada (Gombe)
Musa Kwankwaso (Kano)
Suleiman Nazif (Bauchi)
Lanre Tejuosho
Abdulaziz Murtala Nyako (Adamawa) - ADC
Àwọn ololufẹ BBC News Yoruba fi eroo ọkan wọn ransẹ si wa lori Facebook lori iṣẹlẹ to n waye nile aṣofin Naijiria.
Diẹ lara wọn niyii:
Oladele AfolabiHmmm iru ijọba wo l'anse l'orileede yii, se ijoba amunisin ni abi ijọba olominira? O toju su mi o!.
Abike FetugaO ma’a se Oo.. Kangun kangun,a kangun si bi kan Oo. Oluwa ko ran Orilẹ-ede Nigeria lọwọ.
Folarin OlatunjiBuhari ti mọ wipe osese ti saraki ba darapọ mọ PDP, ewu nla ni fun oun ati wipe wọn le yọ oun nipo..(Impeachment loading)
Ileeṣẹ ọlọpa Naijiria ti ni àwọn ko di ọna ile aarẹ ile aṣofin agba, Bukọla Saraki.
Agbẹnusọ fun ileeṣẹ ọlọpa, Jimoh Moshood, ninu atẹjade kan, sọ pe awọn ko ran ọlọpa kankan lati lọ si ile Bukọla Saraki tabi ti igbakeji rẹ, Ike Ekweremadu.
O fi kun pe dandan ni ki Saraki yọju sileeṣẹ ọlọpa lati wa sọ ohun to mọ nipa idigunjale to waye ni Ọffa.
Bi bẹ ẹ kọ, ileeṣẹ ọlọpa ko ni kuna lati lo agbara ofin lati fi gbe.

Oríṣun àwòrán, NIGERIA POLICE
Ko din ni awọn ọmọ ẹgbẹ oṣelu APC mejilelgbọn, to wa nile aṣofin kekere, to ti fi ẹgbẹ naa silẹ bayii.
Olori ile aṣofin naa, Yakubu Dogara, lo fi ikede naa sita.
Diẹ lara awọn asọfin naa ni:
Funke Adedoyin
Kabiru Marafa
Garba Ibrahim muhammad
Zakari Muhammed
Lawal Rabiu
Orin orisirisi ni awọn ọmọ ile aṣofin naa n kọ lẹyin ikede Yakubu Dogara.
Dogara sọ wi pe adun to wa nibi oselu tiwantiwa ni ki awọn asoju le yan ẹgbẹ to wu wọn.

Oríṣun àwòrán, NASS
Ẹgbẹ oṣelu All Progressives Congress, APC, ti sọ pe inu awọn ko dun si bi àwọn sẹnatọ kan ṣe fi ẹgbẹ naa silẹ, ti wọn si darapọ mọ, PDP.
Agbẹnusọ fun ẹgbẹ naa, Mallam Bolaji Abdullahi, sọ fun BBC pe awọn ti gbiyanju lati ri i pe awọn aṣofin naa ko kuro ninu ẹgbẹ, ṣugbọn, pabo ni igbiyanju naa jasi.
O ni 'àwọn ti ṣetan lati tẹsiwaju ninu irinajo awọn, lẹyin ohun to ṣẹlẹ.'
Ati pe, awọn l'awọn ṣi ni ọmọ ile to pọju lọ ninu ile aṣofin kekere, to fi mọ awọn gomina to pọju ni Naijiria.

Oríṣun àwòrán, APC
Iroyin to n tẹwa lọwọ bayii ni pe ogunlọgọ awọn ọmọ ile aṣofin kekere Naijiria, ti n buwọlu iwe kan gẹgẹ bi igbesẹ lati kuro ninu ẹgbẹ oṣelu APC.
Ṣaaju ni owurọ oni, awọn ọmọ ẹgbẹ oṣelu PDP to wa ni ile aṣofin naa jade sita lati jo, nigba ti wọn gbọ pe awọn ọmọ ile aṣofin agba mẹẹdogun ti fi ẹgbẹ oṣelu APC silẹ bọ si PDP, gẹgẹ bi ẹ ṣe ri i ninu fidio yii.



Ẹgbẹ oṣelu alatako ni Naijiria, Peoples Democratic Party, PDP, ti ki awọn aṣofin agba to fi ẹgbẹ All Progressives Congress, APC silẹ, wa a darapọ mọ PDP.
Agbẹnusọ fun PDP, Kọla Ologbondiyan, lo fi ikede naa sita loju opo Twitter rẹ.
Ọkan lara awọn asọfin to fi ẹgbẹ oṣelu APC silẹ, Dino Melaye, ni ara idi ti oun fi ẹgbẹ naa silẹ ni bi wọn sẹ lo awọn oṣiṣẹ eleto aabo lati fiyajẹ oun.
O ni 'diẹ lo ku ki wọn gba ẹmi mi.'
Ko to o di pe awọn ọmọ ẹgbẹ APC to jẹ aṣofin, fi ẹgbẹ naa silẹ loni, ni ogunlọgọ awọn ọmọ ẹgbẹ ti fi ẹgbẹ naa silẹ, nitori ohun ti wọn pe ni ifiya jẹni.
Diẹ lara wọn ni gomina ipinlẹ Ọṣun nigba kan, Ọlagunsoye Oyinlọla, ati olori oṣiṣẹ fun Saraki, Hakeem Baba Ahmed.

Oríṣun àwòrán, APC
Aarẹ ile aṣofin agba Naijiria, Bukọla Saraki, ti so ijoko ile aṣofin to waye l'oni rọ di ọjọ́ kẹẹdọgbọn, oṣu Kẹsan, lẹyin ti awọn aṣofin kan lati inu ẹgbẹ oṣelu All Progressives Congress, APC, fi ẹgbẹ naa silẹ, ti wọn si darapọ mọ ẹgbẹ, Peoples Democratic Party, PDP.
Ohun to ṣẹlẹ yii ti mu ki awọn ọmọ ẹgbẹ osẹlu PDP, pọ ju awọn ọmọ ẹgbẹ́ APC lọ ni ile aṣofin naa.
Awọn kan to n fi ẹhonu han yabo ile aṣofin Naijiria loni.
Asiko ti awọn asofin n se ijiroro wọn ni wọn yabo ibẹ, ti wọn si n sọ pe ki awọn asọfin ṣe iwadi awọn iṣẹlẹ iṣekupani to n waye ni orilẹ-ede Naijiria.

Iroyin to n tẹ wa lọwọ bayii ni pe ọpọlọpọ awọn sẹnatọ ti fi ẹgbẹ osẹlu to n ṣe iṣakoso lọwọ ni Naijiria, All Progressives Congress, APC, silẹ.
Aarẹ ile aṣofin naa, Bukọla Saraki lo kede igbesẹ awọn sẹnatọ naa.
Orukọ gbogbo wọn niyii:
Sen. Tejouso
Sen. Shaaba
Sen. Gemade
Sen. Melaye.
Sen. Shittu
Sen. Rafiu
Sen. Shitu Ubali
Sen. Isa Misau
Sen. Hunkuyi
Sen. Monsurat
Sen. Danbaba
Sen. Nafada
Sen. Nazif
Sen. Kwankwaso
Abdul-Azeez Murtala Nyako
Àwọn oṣiṣẹ ajọ to n gbogun ti iwa ijẹkujẹ ni Naijiria, EFCC, yii ile igbakeji aarẹ ile aṣofin agba Naijiria, Ike Ekweremadu ka lowur oni.
Ọkan lara awọn amugbalẹgbẹ fun un lori eto iroyin fi idi rẹmulẹ fun BBC pe, ile naa to wa ni adugbo Apo nilu Abuja

Oríṣun àwòrán, UCHE ANICHUKWU