You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́ - 5 Owewe, 2024
Ẹgbẹ awọn akẹkọọ ni Naijiria NANS
Ti kede pe irọ ni iroyin to n lọ nigboro pe awọn fẹ ṣe iwọde latari afikun owo epo bẹntiro
NANS lo sọ ọrọ naa ninu atẹjade kan ti adari rẹ, Akinteye Afeez Babatunde, buwọlu
Babatunde ni ko si ohun to jọ iwọde niwaju awọn lasiko yii
Eemọ wọlu, ọkọ fọ oju iyawo rẹ lorumọju
Ilu Umuahia, nipinlẹ Anambra ni iṣẹlẹ naa ti waye
Amarachi Lawrence ni oju orun loun wa ki ọkọ oun to ki oun mọlẹ lai si ija laarin wọn tẹlẹ
O ṣalaye pe nnkan bii aago kan oru ni ọkunrin naa bẹrẹ si n lu oun, to si n fi ọwọ tẹ oju oun memeji
Obirin naa ti wa nile iwosan bayii, nibi to ti n gba itọju
Ni Uganda
Gbajugbaja elere idaraya kan, Rebecca Cheptegei, ti jde laye lẹyin ti ọrẹkunrin rẹ dana sun-un
A gbọ pe ile ijọsin ni obinrin naa ti n bọ ki iṣẹlẹ ọhun to waye
Iroyin ni ọrọ ilẹ lo da ija silẹ laarin awọn ololufẹ mejeji