You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Biyi Otegbeye: Ìrẹ́jẹ àti ìrìn ìdọ̀tí wà nínú APC l‘Ogun, ni mo ṣe lọ sí ẹgbẹ́ òṣèlu ADC
Oludije sipo gomina labẹ asia ẹgb oselu ADC nipinlẹ Ogun, Olubiyi Oladipupo Otegbeye ti salaye ọpọ ohun to gbe wa sidi oselu ati idi to se fẹ dije du ipo gomina nipinlẹ Ogun.
Otegbeye, lasiko to n fọrọ jomitoro ọrọ pẹlu BBC Yoruba ni irẹjẹ pupọ lo wa ninu ẹgbẹ oselu APC nipinlẹ Ogun nitori ọpọ ohun ti ko bojumu lo waye lasiko ibo abẹnu lati yan oludije sipo gomina ti yoo soju ẹgbẹ naa ninu ibo 2023.
Otegbeye, tii se ọmọ bibi ilu Ilaro, lẹun idibo Ogun West ni kaka ki ohun si maa rin irin idọti ninu ẹgbẹ oselu APC, lo mu ki oun ko aasa oun lọ sinu ẹgbẹ oselu ADC, tii se ẹgbẹ to mọ.
- Wo Aláàfin tó bí ọmọ 1,460, ayaba mẹ́sàn-án bí ìbejì lọ́jọ́ kan ṣoṣo ní ìgbà mẹ́ta
- ''Mó fẹ́ ìpínlẹ̀ Ogun tí àwọn ènìyàn kò ní jíyà nítorí àìsì ìrànwọ́ ìjọba àpapọ̀''
- Wọn kò tíi bí ọkùnrin tí kìí ṣe ṣìná sáyé- Olori Sekinat Elegushi
- Ogun ni ọmọ wẹ́wẹ́ àti aláboyún ti ń kú jùlọ lọ́dún, kò bójúmu - Olùdíje gómìnà AA
- Èmi nipò gómìnà tọ́ sí l‘Ogun, a jọ ṣetò àgbéga ọlọ́pọ̀ ọdún fún ìpínlẹ̀ wa ni - Olùdíje fẹ́gbẹ́ Labour
"Ipe Ọlọrun ni ipe mi sinu oselu, ojuse mi si ni lati mu idagbasoke ba ipinlẹ Ogun nitori pe ẹkun idibo mi n pohungbẹ idagbasoke lo mu mi wọnu oselu.
Amọ bi ibo abẹnu lati yan oludije sipo gomina nipinlẹ Ogun labẹ ẹgbẹ oselu APC se lọ ku diẹ kaa to, a si pe akiyesi awọn alasẹ loke lọhun si sugbọn wọn ko se nkankan si.
Awa mẹfa la dibo abẹnu pẹlu gomina to wa lori oye lọwọ lọwọ, eyiun, Dapo Abiodun, amọ wn ni awa marun ko ni ibo kankan, Abiodun nikan lo ko gbogbo ibo naa.
Koda, awa mẹrin pe ẹjọ kotẹmilọrun lori esi ibo abẹnu naa sugbọn mo finu findọ fi ẹjọ naa silẹ lati lọ dije ninu ẹgbẹ oselu ADC."
Nigba to n sọrọ lori ihuwasi gomina Dapo Abiodun, Otegbeye ni "Bi Abiodun se n bu ramuramu, lo ipo agbara ko mi wa nitori a ti ri awọn eeyan to wa nipo agbara sẹyin, ti wọn se ju bẹẹ lọ.
Abiodun ti ko awọn ọba ladelade wa laya jẹ, o ti sọ wọn di oloselu, se lo n ko wọn lẹyin lọ sode oselu, o kan ku diẹ, ki wọn maa de fila ipolongo ibo Abiodun ni."
Bakan naa ni oludije sipo gomina fẹgbẹ oselu ADC ọhun salaye ajọsepọ to wa laarin ohun ati gomina ipinlẹ Ogun tẹlẹ, Ibikunle Amosun ati ọpọ ohun ribiribi to fẹ gbe se lori oye, to ba wọle sipo gomina ipinlẹ Ogun.
- 'Ẹ̀rú bà mí lọ́jọ́ tí mo wọ bọ́ọ̀sì dẹ́rẹ́bà ọlọ́wọ́ kan lọ Ilorin', ìrírí àwọn èrò ọkọ̀ rèé
- Ṣé lóòótọ́ ní Kayamata jẹ́ àdódùn àti òògùn ìbílẹ̀ tí wọn fi ń so ọkùnrin mọ́lẹ̀?
- ''Mó fẹ́ ìpínlẹ̀ Ogun tí àwọn ènìyàn kò ní jíyà nítorí àìsì ìrànwọ́ ìjọba àpapọ̀''
- Ikorodu Bois: Ko si ẹni ti a kò lè sín jẹ!
- Ikú dóró! Èèyàn tó jẹ́ Ọlọ́run nípè níbi ìbúgbàmú Mọsalasi Pakistan ti di 100