Kannywood Kidnapping: 'Mọ́ngòrò nìkan ni wọ́n fún mi jẹ ní àhámọ́ ajínigbé'

Oríṣun àwòrán, Salisu Muazu/Facebook
Gbaju-gbaja oludari ere Kannywood ti awọn ajinigbe tusilẹ lọjọ Abamẹta, Salisu Muazu ti sọ fun BBC pe mọngoro nikan ni awọn ajinigbe naa fun oun ati ọrẹ mẹta ti wọn jigbe jẹ fun ọjọ mẹta.
Oludari ere ọhun to n gbe niluu Jos lo n rinrinajo lọ si ipinlẹ Plateau lati Kaduna lọjọbọ to kọja pẹlu aburo rẹ, ati awọn ọrẹ nigba ti awọn ajinigbe naa da wọn lọna.
"Ile ti wọn fi wa si ko ni orule rara. Ori wa ni ojo n rọle, mọngoro nikan si ni wọn n ka fun wa jẹ lori igi kan to wa nitosi ibẹ fun ọjọ mẹta."
"Awọn ajinigbe naa sọ fun wa pe awọn yoo san owo ibọn AK47 ti awọn ya, owo ọga wọn lara miliọnu mẹwaa Naira ti a ba san."
Muazu ṣalaye pe awọn ajinigbe naa sọ fun awọn pe awọn kan to wa ni ipo pataki n lọwọ si awọn ijinigbe to n waye ni Naijiria.

Oríṣun àwòrán, Salizu Muazu
Muazu sọ pe gẹgẹ bi oludari ere, oun yoo lo iriri naa lati ṣe sinima ti yoo gba ami ẹyẹ fun oun.
Miliọnu mẹwaa Naira ni mọlẹbi Muazu san ki wọn o to tu wọn silẹ.
Ojoojumọ ni iroyin ijinigbe n jade lorilẹ-ede Naijria, botilẹjẹ pe ọga agba ileeṣẹ ọlọpaa sọ laipẹ yii pe o ti dinku lẹyin ti awọn ọlọpaa so okun aa bo le lawọn opopona nla.
- Àwọn bàbá ìsàlẹ̀ òṣèlú tó bá ìtìjú bọ̀ nínú ìbò Gómìnà rèé
- Afurasi tó fa ìpayà nílé ìwé Port Harcourt ti wọ gàù
- Ọ̀rọ̀ Aisha Buhari sí Ramaphosa wú ọ̀rọ̀ síta lẹ́nu àwọn ọmọ Nàìjíríà
- Kí ló ṣe ikú pa Adediwura Lateefat Bello lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ méjì tí wọ́n ń wá a?
- Kí ló yẹ kí Àyájọ́ ọjọ́ àwọn èwe Nàìjíríà lọ́dún yìí dá lé lórí?















