Ọbasanjọ ni ko jẹ k'awọn ọdọ de'po - Ogundamisi
Onwoye awujọ kan, Kayọde Ogundamisi ti ni Oloye Olusegun Ọbasanjọ lo ba Naijiria de ibi to de yi.
O ni ko yẹ ki Ọbasanjọ maa gbe ẹnu sọrọ Naijiria mọ nitoripe ko fun awọn ọdọ laaye lati de ipo nigba to wa lori aleefa gẹgẹ bii aarẹ orilẹede yii.
Bakanaa lo woye pe wọn ko tii gbe oludije takuntakun kankan kalẹ to lee fi ẹyin Aarẹ Muhammadu Buhari janlẹ bio ti lẹ je oun ko faramọ isejọba Buhari.