Adebayo Shittu: Èmi kò ṣẹ Abiola Ajimobi nígbà ayé ẹ, òun ló ṣẹ̀ mi ṣùgbọ́n.....

Ajimobi maa n ni pe Shittu le pupọ. mo kan kọ irẹjẹ ati iwọsi ni- Adebayo Shittu

Minista ọrọ ibaraẹnisọrọ ni Naijiria tẹlẹ, Amofin Adebayo Shittu gba BBC lalejo nile rẹ.

Ninu ifọrọwanilẹnuwo naa lo ti sọ ohun to ṣẹlẹ laarin rẹ ati oloogbe Abiola Ajimobi to jẹ gomina ipinlẹ Oyo tẹlẹ ati ibi ti ọrọ de duro pẹlu Florence, aya gomina Ajimobi bayii.

Amofin Adebayo Shittu ni nitori pe Ajimobi kọ lati jẹ ki oun rọpo rẹ nipo gomina lo bi ige ati Adubi to pada ṣẹlẹ.

O ni o dun oun pe ko si agbaagba ẹgbẹ APC kankan to ba wọn da si ija naa nitori ipo. agbara ati owo ti gomina ni.

Shittu ni Ilosiwaju ipinle Oyo lo ku to yẹ ko jẹ gbogbo awọn to ku laye to n wa ni ipo oselu ni ipinlẹ Oyo logun lasiko yii.

O ni pe nitori ko sẹni ti ko ni ku lọrọ ọhun.

Adebayo Shittu sọ bi oun ati baba Ganiyu Ajimobi to jẹ baba gomina Abiola Ajimobi ṣe jọ wa nile igbimo asofin ni Oyo nigba naa ati bi Baba Ganiyu Ajimbi se mu oun bii ọmọ.

O ni oun ati Ajimobi pada ri ara wọn ko to ku.

O parọwa pe ki agba oloselu mu ilọsiwaju awọn eeyan rẹ lọkunkundun.