Ijoba Eko: Akọ́ni mánigbàgbé ni Abiola
ìpínlẹ̀ Èkó sọkutu wọ̀wọ̀ ní àyájọ́ ‘June 12’ fún tọdún yìí, nígbàtí Ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó sí ère kan tí wọn fi ń se ìrántí olóògbé MKO Abiọla ní àyájọ́ ìdìbò June 12.
Yorùbá ní, báa kú làá dère, èèyàn kò sunwọ̀n ní ààyè, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ olóògbé MKO Abiọla rí, tí ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó sì ń bèèrè pé kí wọn fi fọ́nrán àwòrán àti ohùn ìgbà ìkẹyìn olóògbé Abiọla síta.