Àyájọ́ ọjọ́ ìjọba Tiwa n' tiwa: Kókó mẹ́wàá nínú ọ̀rọ̀ Buhari

Àárọ̀ kùtù ojọ́ ẹtì ni Ààrẹ orílẹ̀ èdè Naijíría, Muhammadu Buhari ka ọ̀rọ̀ àpilẹ̀kọ rẹ̀ ní ayajọ́ ọjọ ìjọba tiwa n' tiwa.

Nínú ọ̀rọ̀ náà Buhari sọ nípa gbogbo àwọn àṣeyọrì rẹ̀ láti ìgba tí ó ti gba ìjọba.

Ṣùgbọ́n, kíì ṣe gbogbo ọmọ Naijiria ni ó gbágbọ́ pé bí ààrẹ ṣe sọ́ ọ ni ó rí. Ní kété tí ó ka ọrọ àpilẹ̀kọ rẹ̀ ni ọpọlọpọ̀ bẹ̀rẹ̀ sí na ìka àlébù si i lórí ìkànnì Twitter.