You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.

Take me to the main website

Lucky Aiyedatiwa olùdíje ẹgbẹ́ òṣèlú APC wọlé ìbò gómìnà ìpínlẹ̀ Ondo

Lapapọ ibo 366,781 ni Aiyedatiwa ri nigba ti Agboola oludije PDP to ṣe ipo keji ninu eto idibo naa ri 117,845.

Ìsọníṣókí

Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tí ń lọ lọ́wọ́

Joshua Adetunji, Busayo James-Olufade, Afolabi Akinlabi

  1. Gbogbo ìlérí tí mo ṣe lásìkò ìpolongo ìbò ni mà á múṣe - Aiyedatiwa

    Gómìnà tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ dìbò yàn ní ìpínlẹ̀ Ondo, Lucky Orimisan Aiyedatiwa ní ìjáwe olúborí òun níbi ètò ìdìbò náà túmọ̀ sí pé òun gbọdọ̀ mú àlékún bá iṣẹ́ tí òun ń gbé ṣe fáwọn èèyàn ìpínlẹ̀ náà.

    Aiyedatiwa ló sọ èyí nígbà tó n bá àwọn akọ̀ròyìn sọ̀rọ̀ lẹ́yìn tí àjọ tó ń rí sí ètò ìdìbò ní Nààijíríà, INEC kéde rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹni tó jáwé olúborí ètò ìdìbò sípò gómìnà lọ́jọ́ Àbámẹ́ta.

    Ó ní gbogbo ìbú àti òró ìpínlẹ̀ Ondo ni òun ṣe àbẹ̀wò lásìkò tí òun ń ṣe ìpolongo ìbò, tí èyí sì jẹ́ kí òun mọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan táwọn èèyàn ìpínlẹ̀ náà ń fẹ́.

    Ó sọ pé kí àwọn èèyàn ìpínlẹ̀ náà lọ fi ọkàn balẹ̀ nítorí òun máa ṣe àrídájú rẹ̀ pé àwọn èèyàn náà rí èrè ìṣèjọba àwaarawa.

    Ó fi kun pé gbogbo bí nǹkan ṣe rí ní àwọn agbègbè tí òun dé lásìkò ìpolongo ìbò ni òun mọ̀ tí òun yóò sì ri pé gbogbo àwọn tó nílò àtúnṣe ni ọwọ́ ìjọba yóò dé.

    “Ní gbogbo ìlú tí mo dé lásìkò ìpolongo ìbò, mo rí bí ọ̀nà wọn ṣe rí, mo rí bí àyíká tí wọ́n ń gbé ṣe rí, mo gbọ́ oùn wọn, tí mo sì fèsì sí gbogbo ìbéèrè wọn.

    “Mo ní ìgbàgbọ́ pé wọ́n ní ìrètí nínú mi ni wọ́n ṣe dìbò fún mi, gbogbo nǹkan tí mo ṣèlérí lásìkò ìpolngo ìbò náà ni mà á ṣe fún wọn.”

  2. Lucky Aiyedatiwa olùdíje ẹgbẹ́ òṣèlú APC wọlé ìbò gómìnà ìpínlẹ̀ Ondo

    Ajọ eleto idibo INEC ti kede Lucky Orimisan Aiyedatiwa oludije ẹgbẹ oṣelu APC gẹgẹ bi ẹni to jawe olubori ninu eto idibo gomina ipinlẹ Ondo to waye lana ọjọ Abamẹta.

    Aiyedatiwa la oludije ẹgbẹ oṣelu PDP, Ajayi Agboola, mọlẹ lati bori ninu eto idibo naa.

    Gẹgẹ bi esi ibo ti ajọ INEC kede, gbogbo ijọba ibilẹ mejidinlogun to wa ni ipinlẹ Ondo ni Aiyedatiwa ti jawe olubori.

    Lapapọ, ibo 366,781 ni Aiyedatiwa ri nigba ti Agboola to ṣe ipo keji ninu eto idibo naa ri 117,845.

    Adeyemi Nejo to jẹ oludije ẹgbẹ Oṣelu ADC to ṣe ipo kẹta ri ibo 4,138.

  3. Aiyedatiwa àtàwọn gómìnà APC ń retí ìkéde èsì ìdìbò ìpínlẹ̀ Ondo

  4. Ẹgbẹ́ òṣèlú APC, PDP ra ìbò, àwọn agbófinro gan lẹ̀dí àpò pọ̀ - Yiaga

    Bi eto idibo gomina ni ipinlẹ Ondo ṣe n waye lọjọ Abamẹta, wọn ti tọka si awọn ẹgbẹ oselu kan pe wọn n ra ibo pẹlu owo ti iye rẹ to ẹgbẹrun marun un si ẹgbẹrun lọna ogun naira.

    Ọkan lara awọn ẹgbẹ ajafẹtọ araalu kan to seamojuto idibo naa, Yiaga Africa ṣalaye pe ọkan o jọkan iwa to lodi si ofin lo n waye lasiko idibo naa, ti wọn si n ke si ajọ INEC atawọn adari abo lati tete wa nnkan ṣe sii.

    Ninu ọrọ ti wọn ba awọn akọroyin sọ nilu Akurẹ lori ohun ti oju wọn ri kaakiri tibu toro ipinlẹ naa l’ọjọ Abamẹta Ọgbẹni Ezenwa Nwagwu ni awọn ri awọn qgbofinro kan ti wọn n lẹdi apo pọ pẹl’awọn to n ra ibo ni Ilara, Ilẹoluji at’awọn agbegbe miran.

  5. Ọkùnrin kan tó ‘jí àpótí ìbò gbé’ nílùú Idanre jẹ àjẹtún ìyà

    Alubami ni wọn lu ọkunrin kan ti wọn sọ pe o ji apoti ibo gbe ni ibudo idibo gomina ipinlẹ Ondo to wa ni ile ẹkọ girama Methodist High School niluu Idanre.

    Awọn ọlọpaa lo gba ọkunrin naa silẹ lọwọ awọn eeyan to n dawọ jọ lu u ti wọn si mu wọ inu ọkọ wọn.

  6. Ìdìbò ti parí ní àwọn ibùdó ìdìbo kan nipinlẹ Ondo

    Eto idibo ti pari ni awọn ibudo idibo kan niluu Idanre, ti awọn oludibo si n duro fun kika.

    Bakan naa, akọroyin BBc to wa niluu Akure sọ pe, ida kan ninu meji awọn ibi ti idibo ti waye, ni wọn ti dibo tan.

    O ni awọn oludibo ko fi bẹẹ jade dibo.

    Amọ o, ajọ INEC sọ fun BBC pe awọn yoo duro di aago meji-aabọ ọsan lati mọ boya awọn eeyan yoo ṣi jade wa.

  7. Báyìí ni àwọn olùdìbò àti àwọn aṣojú ẹgbẹ́ òṣèlú ṣe n ṣe kárà-kátà ìbò nílùú Owo, nínú ìdìbò gómìnà tó n wáyé.

    Fidio to wa ni isalẹ yii lo n ṣafihan bi awọn oludibo ati ẹgbẹ oṣelu kan ṣe n ṣe karakata ibo.

    Ibudo idibo 'Unit 016', Ahmadiyya Grammar School, Owo nibi ti igbakeji gomina ipinlẹ Ondo, Olayide Adelami, ti dibo ni eyi ti waye.

    Amọ ṣa, kii ṣe lasiko ti Ọgbẹni Adelami wa a dibo ni eyi waye.

    Bakan naa ni a ko le sọ pato ẹgbẹ osẹlu to n fi owo ra ibo.

  8. Ẹ wo bí àṣírí àwọn tó n ṣe kárà-kátà ìbò ní Idanre tú sí BBC lọ́wọ́, Òṣìṣẹ́ INEC tú àṣírí akọ̀ròyìn BBC tó n àwòran fún àwọn tó n ṣe kárà-kátà ìbò ní Idanre

    BBC Yoruba le fidi rẹ mulẹ pe iṣẹlẹ ‘dibo ko sebẹ’ waye niluu Idanre nibi ibo gomina ipinlẹ Ondo to n lọ lọwọ.

    Akọroyin BBC Yoruba to wa ni ibudo idibo kan jabọ pe ni ṣe lẹgbẹ oṣelu APC n fawọn eeyan ni N10,000 lati dibo fun wọn.

    Gẹgẹ bi ohun ti akọroyin BBC Yoruba ri, aṣoju ẹgbẹ oṣelu APC kan lo n pin owo naa fawọn oludibo to ba ti dibo tan, to si fi iwe idibo rẹ han lati ṣami pe ẹgbẹ naa lo dibo fun.

    Oludibo kan to gbowo lẹyin to dibo sọ fun BBC Yoruba wi pe ọbẹ Turkey l'oun yoo fi owo naa se.

    "Ọmọbinrin to gbowo yii tun mu aburo rẹ naa wa lati wa gbowo tiẹ naa, amọ, aṣoju to n pin owo kọ lati fun aburo rẹ lowo nitori ko fi iwe idibo rẹ han an.

    Bayii ni ọmọbinrin naa bẹrẹ si ni ṣẹ epe ti o si sọ pe oun kan ṣe wahala lasan wa dibo ni lai yọ owo kankan.

    Nibi ti akọroyin BBC ti n gbiyanju lati ya fidio awọn to n ṣe kara-kata ibo yii, ni oṣiṣẹ ajọ INEC kan ti ri i, to si sọ fun awọn to n hu iwa yii.

  9. 'Mo ní ìgbàgbọ́ pé nnkan yóò ṣì dára ni mo ṣe jáde dìbò'

  10. Àwọn òṣìṣẹ́ àjọ EFCC ṣe ìkìlọ̀ fún àwọn olùdìbò

  11. Gómànà Lucky Aiyedatiwa ti dìbò

    Gomina ipinlẹ Ondo, Lucky Aiyedatiwa, ti dibo ni ilu abinibi rẹ niluu

    Aiyedatiwa n dije lati tẹsiwaju gẹgẹ bi gomina ipinlẹ naa, lẹyin to de ipo naa nigba ti ọga rẹ, Gomina Rotimi Akeredolu, ku.

    Ibudo idibo Ugbonla Ward 4 Unit 5, ni ijọba ibilẹ Ilaje.

  12. Ìdìbò ti bẹ̀rẹ̀ ní àwọn ibùdó kan ní ìlú Idanre

    Ninu eto idibo gomina ipinlẹ Ondo to n lọ lọwọ, idibo ti bẹrẹ ni ibudo idibo kẹrin, eyi to wa ninu ọgba il-ẹkọ Methodist High school, niluu Idanre.

  13. Olùdíje méjìdínlógún ló n kópa nínú ìdìbò gómìnà ìpínlẹ̀ Ondo

    Oni, ọjọ Satide, ọjọ kẹrindinlogun, oṣu Kọkanla, ọdun 2024, ni eto idibo sipo gomina ipinlẹ Ondo yoo waye.

    Ajọ eleto idibo, INEC, sọ pe 2,053,061 miliọnu oludibo lo fi orukọ silẹ jakejado ipinlẹ naa.

    Ninu eto idibo ọhun, oludije mejidinlogun lo n kopa, ninu eyi taa ti ri gomina to wa nipo, Lucky Aiyedatiwa. Orukọ awọn oludije ọhun pẹlu ẹgbẹ osẹlu wọn

    • Lucky Aiyedatiwa of APC
    • Agboola Ajayi of PDP
    • Sola Ebiseni for LP
    • Abbas Mimiko of ZLP
    • Falaiye Abraham Ajibola - A
    • Akinuli Fred Omolere - AA
    • Ajayi Adekunle Oluwaseyi - AAC
    • Nejo Adeyemi - ADC
    • Akinnodi Ayodeji Emmanuel - ADP
    • Populqa Olatunji Tunde - APGA
    • Ogunfeyimi Isaac Kolawole - APM
    • Fadoju Amos Babatunde - APP
    • Olugbemiga Omogbemi Edema - NNPP
    • Ajaunoko Funmilayo Jenyo - NRM
    • Alli Babatunde Francis - PRP
    • Akingboye Benson Bamidele - SDP
    • Adegoke Kehinde Paul - YP
    • Akinmurele John Otitoloju - YPP

    Ẹ ma jina si oju opo yii lati mọ bi idibo naa ṣe n lọ.

  14. Gbogbo ètò ló ti tò báyìí fún ìdìbò gómìnà ìplínlẹ̀ Ondo láti gbérasọ

    Ajọ eleto idibo INEC ti pin ohun elo idibo kaakiri gbogbo ijọba ipinlẹ to wa nipinlẹ Ondo ṣaaju eto idibo gomina ti yoo waye lọla ọjọ Abamẹta nipinlẹ naa.

    Ni ẹka ileeṣẹ ifowopamọ apapọ Naijiria, CBN, to wa lagbegbe Alagbaka niluu Akure ni ajọ INEC ti ko awọn nnkan elo idibo lọ kaakiri gbogbo ijọba ibilẹ nipinlẹ Ondo.

    Ẹwẹ, ijọba ìpínlẹ̀ Ondo ti kede òní, ọjọ karundinlogun, oṣù Kọkànlá, ọdún 2024, gẹgẹ bíi ọjọ ìsinmi lẹnu iṣẹ fún àwọn oṣiṣẹ ipinlẹ náà ṣaaju ìdìbò gomina ti yóò waye nibẹ.

    Nínú atẹjade kan lati ọọfisi olórí oṣiṣẹ, O. F. Ayodele, sọ pé igbesẹ naa ko sẹyìn ki awọn oṣiṣẹ ọhun le rí aye rìnrìn àjò lọ ilu wọn láti dibo.

    Ọla, ọjọ Abamẹta, ọjọ kẹrindinlogun, oṣù Kọkànlá, ọdún 2024 ni eto ìdìbò náà yoo wáyé.

    Káàkiri ìjọba ìbílẹ̀ mejidinlogun to wa ni ipinlẹ Ondo ni ìdìbò ọhun yoo ti wti wáyé.

    Ẹgbẹ òṣèlú merindinlogun lo yẹ kí wọn kopa nínú ìdìbò náà ṣaaju asiko yii.

    Ṣugbọn, nigba ti ìdìbò náà kù ọjọ meji pere ní ẹgbẹ oṣelu mẹta ju ọwọ silẹ fún Lucky Aiyedatiwa,to n dije labẹ asia ẹgbẹ oṣelu APC.