Olubadan stool: Rashidi Ladoja ní àṣà ilẹ̀ Ibadan kò nó dàrú lórí òun

Mọ̀ síi nipa ǹkan tí Gomina Abiola Ajimobi fún àwọn Oloye 21 nàá ti wọ́n fi gbà láti dé Adé láìnáání àṣà Ibadan- Amofin Lana

Lori awuyewuye awọn eniyan ilu Ibadan lati mọ ẹni ti ade Olubadan kan naa ni BBC Yoruba jade lo ba awọn eekan ti ọrọ naa ṣoju wọn sọrọ.Ajimobi kò déédé yan Oba 21, àwọn àgbààgbà ilẹ̀ Ibadan ló bẹ̀ẹ́ láti gbé ìgbésẹ̀ náà- Omowe Gbade Ojo

Amofin Michael Folorunso Lana to ṣoju awọn oloye Ibadan lati kọkọ ṣe lodi si igbesẹ gomina ana ni ipinlẹ Oyo, oloogbe Abiola Ajimobi naa sọ ohun to mọ nipa ọrọ naa lati ibẹrẹ.

O ni Ajimobi lo da ọrọ oye naa ru nigba naa.

Amofin Lana ni agbejoro Olubadan Council nigba ti ọrọ yii ṣẹlẹ

Orí tèmi kọ́ ni àṣà Ibadan yóò ti dàrú- Rashidi Ladoja

Omowe Ojo ni pe awọn arugbo ti ko kawe ni Ajimobi ko fẹ mọ lo ṣe gbe igbesẹ to gbe ki awọn ọdọ to kawe naa le bẹrẹ lati ori oye Mogaji.

Eni ti Oba ba kan ni yoo jọba bayii lẹyin ti Oba Saliu Adetunji ti gbesẹ ni ọrọ Omowe Ojo.

O ni ko si auyewuye nibẹ rara.