You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Dálémoṣú ni mí ṣùgbọ́n ó ní ìdí - Adaku inú eré Jẹnifa
Kìí ṣe gbogbo Dalemoṣu lo n ṣe aṣẹwo - Adaku
Omotunde Adebowale ni orukọ abisọ ti oṣere to tun jẹ sọrọsọrọ ti igba oju mọ ti wọn n pe ni Adaku ninu eré Jẹnifa.
BBC Yorùbá gbalejo Adaku ninu ile iṣẹ wa nibi to ti sọrọ ni kikun lori ikọraẹnisilẹ.
Adaku ni ẹnu araye lẹbọ ninu ọrọ igbeyawo nitori wọn a ni ki lode too ṣe sọrọ sita tabi o kuku ti n sọrọ ju.
Oṣere yii royin oun ti oju obinrin to ti kọ ọkọ silẹ n ri lawujọ Yoruba.
O ni ọpọ ninu awọn ọrẹ ni ọkọ wọn ni ki wọn yẹra fun mi bẹẹ ko si ẹni to wù láti dalemoṣu laye.
Adaku ni awọn eeyan maa n sọ pe awọn ọmọ obinrin ti ko si nile ọkọ ko le yanju ṣugbọn Olorun ju ẹda lọ.
O ni oju ẹni to kọ ọkọ rẹ silẹ n ri to!
Adaku ṣalaye iru eeyan ti Funkẹ Akindele jẹ pẹ kii fi iṣẹ rẹ ṣere koda a le sọ pe ó burú.