You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Obasanjo: Atiku kìí se Áńgẹ́lì, àmọ́ yóò se dáadáa ní ìlọ́po méjì ju Buhari lọ
Aarẹ tẹlẹ ni orilẹede Naijiria, Oloye Oluṣẹgun Ọbasanjọ, lasiko to n ba BBC Yoruba sọrọ, mẹnuba pe, Buhari lo buwọlu ofin pe awọn ọdọ lee dije fun ipo aarẹ, amọ ti oun naa wa n dije lẹni ọdun mẹrindinlọgọrin,
Ọbasanjọ ni ko si ẹni to pe, ni oun se darijin oludije fun ipo aarẹ ninu ẹgbẹ oselu PDP, Atiku Abubakar, niwọn igba to ti wa bẹbẹ, ki Ọlọrun lee dari awọn ẹsẹ ti oun naa jin oun.
Aarẹ nigba kan ri naa fikun pe, Atiku yoo se daada ni ilọpo meji ju Muhammadu Buhari to wa nipo aarẹ bayii lọ, nitori ẹsẹ awọn eeyan to n dari wa loni gan pọ, ta ba si ni ka tu ẹsẹ wọn sita, wọn yoo wọna, yatọ si pe wọn yoo wọ ẹwọn, wọn yoo tun wọ ina.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ẹgbẹ́ alátakò fẹ́ lo Boko Haram láti da ìbò 2019 rú - Lai Muhammed
- Irú kan náà ni Atiku àti Buhari, kò s'íyàtọ̀ nínú wọn - Tunde Bakare
- Ẹ̀rò àwọn ènìyàn se ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ lórí lẹ́tà Ọbasanjo sí Buhari
- Ọbasanjọ: Ó yẹ kí Amina Zakari kọ̀wé fipò sílẹ̀
- Kíni ìwọ mọ̀ nípa Funmilayọ Ransome-Kuti?
- Ẹfunsetan Aniwura, obìnrin tó ju ọkùnrin lọ
- Hubert Ogunde rèé, baba àwọn òsèré tíátà
- Kí lo fẹ́ mọ̀ nípa ‘Ajala Travels’?
- Wòlíì Kasali ní Dolapo Awosika kò lé ìyàwó òun jáde
- 'Alífábẹ́ẹ́tì Ohùn Oduduwa di ìtẹ́wọ́gbà ni Ajaṣẹ'
Ọbasanjọ ni, Buhari ko ni igbẹkẹle ninu ẹya miran lati baa sisẹ, ju awọn ibatan rẹ nidi iya ati baba lọ.
O fikun pe, niwọn igba ti Buhari ko ti ni igbẹkẹle ninu ẹya miran, ko yẹ ko beere ibo lọwọ wọn, tori bu fun mi, ki n bu fun ọ ni ọpọlọ nke loke odo.
Ẹwẹ, ijọba apapọ ti fesi si awọn ẹsun ti Oloye Olusẹgun Ọbasanjọ sọ nipa ijọba Muhammadu Buhari .
Amugbalẹgbẹ Buhari feto iroyin, Garba Shehu, nigba to n fesi sawọn ẹsun naa naa ni irọ lasan ni Ọbasanjọ n pa lori awọn ẹsun naa.
O fikun pe Ọbasanjọ n jowu ni, ti ọpọlọ rẹ ko si da pe mọ, bẹẹ lo ni Ọbasanjọ nilo lati l ri dokita.