You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Àwọn t'Ojuẹlẹgba l'Eko sọ̀rọ̀ nípa iṣẹ́ oògùn olóró lára
Wo bí oògùn olóró ṣe ń fèèyàn dábírà!
BBC Yoruba bá díẹ̀ lara àwọn to n lo oogun oloro nibudokọ 'Under Bridge' ni Ojuẹlẹgba nipinlẹ Eko sọrọ lori àṣilo oogun oloro.
Awọn eeyan ìdíkọ̀ naa gba pe iṣẹ́ burúkú ni oògùn olóró n ṣe lara wọn.
Wọn mẹnuba oriṣii ọna ti onikaluku wọn n gba lo oogun oloro ati orukọ irufẹ eyi ti wọn n mu.
Oògùn olóró, ọmọ ìyá Codeine
Orilé-ede Naijiria ti fofin de gbigbe Codeine wọle lẹyin iwadii ile iṣẹ wa (BBC) lori bi àwọn ọdọ ṣe n ṣìí lo.
Ṣugbọn igbesẹ yii nikan kọ lo le fopin si àṣìlò oogun oloro ni Naijiria.
Awọn dokita to n ba awọn to n lo oogun oloro sọrọ ni Ojuẹlẹgba naa mẹnuba ọna abayọ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
Ọpọlọpọ àwọn ọ̀dọ́ lo ti lùgbàdì aṣilo oogun nipa ẹgbẹ́kẹ́gbẹ́ àti àìní àbójútó àwọn òbí ati alagbatọ.
Bẹẹ, Yoruba gbà pé, ọmọ ti a kò tọ́ ni yoo gbe ilé ti a kọ́ tà lẹyin ọ̀la.